18/08/2026
Nkan dee! Ilé ìwòsàn kọ Taiwo Hassan Ogogo láti tọ́jú, nítorí pé òní Àìsàn jẹjẹrẹ (Cancer), ọmọ rẹ bù ṣẹkún.
Ọ̀kan lára àwọn oṣèré Nollywood olókìkí ní Nàìjíríà, Hassan Taiwo, ẹni tí a mọ̀ sí Ogogo, ti ní àyẹ̀wò tí ó fi hàn pé ó ní àrùn jẹjẹrẹ (Cancer) tí ó sì ti dé ipele kẹrin.
Ọmọ Ọmọbìnrin rẹ̀, Kira Taiwo, ló fi ọ̀rọ̀ náà hàn ni gbangba nínú fídíò kan tó tan káàkiri lórí ayélujára ní ọjọ́ Mọ́ndé, níbi tó ti bẹ àwọn ọmọ Nàìjíríà pé kí wọ́n ràn baba rẹ̀ lọ́wọ́.
Kira ṣàlàyé pé ìrànlọ́wọ́ tí wọ́n ń wá kì í ṣe owó, ṣùgbọ́n ohun tí wọ́n nílò ni ìrànlọ́wọ́ láti mọ ibi tó yẹ kí wọ́n ti gba ìtọ́jú tó péye fún baba rẹ̀.
Ó ní ilé ìwòsàn tí Ogogo ti ń gba ìtọ́jú tẹ́lẹ̀ ti kọ̀ láti tẹ̀síwájú pẹ̀lú ìtọ́jú rẹ̀. Nítorí náà, wọ́n ń wá ibo míràn tí wọ́n lè ti tọ́jú rẹ̀, bóyá ní ilé ìwòsàn tàbí nípasẹ̀ ìtọ́jú ìbílẹ̀.
Kira tún sọ pé ìkùn baba oun ti wú, èyí sì ti mú kí àìsàn na lágbára si.
Ó tún ṣàfihàn pé Senator Olamilekan Adeola, ẹni tí wọ́n mọ̀ sí Yayi, tó jẹ́ olùdíje fún ipò gómìnà Ogun State lábẹ́ APC nínú ìdìbò ọdún 2027, ti ń san owó ìtọ́jú Ogogo.
Gẹ́gẹ́ bí ìròyìn náà ṣe sọ, àwọn ìgbìmọ̀ láti gbé Ogogo lọ sí ilẹ òkèèrè fún ìtọ́jú, kò ṣàṣeyọrí, nítorí pé àwọn dókítà ti sọ pé kò yẹ fún un láti rìnrìn-àjò jáde kúrò ní orílẹ̀-èdè Nàìjíríà ní ipò tí ara rẹ̀ wà báyìí.
Kira bẹ̀bẹ̀ pé bí ẹnikẹ́ni bá mọ̀ ilé ìwòsàn, ẹgbẹ́ dókítà, àjọ tàbí ẹni kọọkan tó lè pèsè ìrànlọ́wọ́ fún baba oun, kí irú ẹni bẹ́ẹ̀ jáde wá.
Ó ní gbogbo ìrànlọ́wọ́, àdúrà àti àtìlẹ́yìn ẹyin olólùfẹ́ baba oun ṣe pàtàkì fún wọn.
“Kí Ọlọ́run fún un ní ìwòsàn àti agbára.” Àmín