Iwe Iroyin Yoruba

Iwe Iroyin Yoruba Ẹ káàbọ̀ sí Ìkànnì Ìwé Ìròyìn Yorùbá fún ìgbélárugẹ àwùjọ Yorùbá.Aǹfààní wà láti mọ̀ nípa ilẹ Yòrùbá.

Kwam1 la ń rán lọ́wọ́, Kwam2 ti ṣẹlẹ̀ báyìí, ṣé ká máa retí Kwam 3?
11/08/2025

Kwam1 la ń rán lọ́wọ́, Kwam2 ti ṣẹlẹ̀ báyìí, ṣé ká máa retí Kwam 3?

Ilé iṣẹ́ ọkọ̀ òfurufú Ibom Airlines ti fi òfin de arábìnrin Comfort Emmanson lẹ́yìn ìtakàngbà tó wáyé láàárín òun àti àwon òṣìṣẹ́ rẹ̀. Títí ayérayé ni Comfort ò ní le lo ọkọ̀ òfurufú Ibom Air mọ́. Nínú fọ́nrán tó gbòde kan ni a ti ...

ÀWỌN ABARAPÁ ṢE ÌWỌ́DE ILÉ ÌWÉ WỌN TÓ WÀ NI TÍTÌ PA.Àwọn abarapá ní ìpínlẹ̀ Èkó tú jáde láti ṣe ìwọ́de látàrí bí ilé ìwé...
11/08/2025

ÀWỌN ABARAPÁ ṢE ÌWỌ́DE ILÉ ÌWÉ WỌN TÓ WÀ NI TÍTÌ PA.

Àwọn abarapá ní ìpínlẹ̀ Èkó tú jáde láti ṣe ìwọ́de látàrí bí ilé ìwé wọn ṣe wà ní títìpa. Wọ́n dí gbogbo ọ̀nà tó lọ sí pápákọ̀ òfurufú Muritala Muhammed.
Ohun tí wọ́n ń bèèrè fún náà ni kí ìjọba ó ṣí ilé ìwé àwọn tó ti wà ní títìpa láti ọdún méjì sẹ́yìn.
Wọ́n ṣe àlàyé pé ojú alágbe ni àwọn èèyàn fi ni wo àwọn nítorí pé àwọn kò ní anfààní àti kẹ́kọ̀ọ́.
Ìjọba wá kọ́ ilé ìwé fún àwọn sí Isheri, wọ́n sì tún tì í pa láti ọdún méjì sẹ́yìn láìní ìdí kankan.
Wọ́n ní àwọn ti kọ lẹ́tà títí kò sí èsì kankan ni àwọn ṣe ṣe ìwọ́de yìí, èyí yóò kan ìjọba lára wọn yóò sì dá àwọn lóhùn.

IGBÉKEJÌ AKỌ́NIMỌ̀Ọ́NGBÁ IKỌ̀ SHOOTING STARS; OLOWOOKERE TI DÁGBÉRE FÁYÉ.Igbákejì akọ́nimọ̀ọ́ngbá ikọ̀ Shooting stars; A...
11/08/2025

IGBÉKEJÌ AKỌ́NIMỌ̀Ọ́NGBÁ IKỌ̀ SHOOTING STARS; OLOWOOKERE TI DÁGBÉRE FÁYÉ.

Igbákejì akọ́nimọ̀ọ́ngbá ikọ̀ Shooting stars; Akin Olowookere ṣubú lulẹ̀ níbi ìgbaradì ó sì dágbére fáyé.
Kò sí àlàyé kan lórí ikú rẹ̀ ju pé ó ṣubú lulẹ̀ níbi tí wọ́n ti ń gbaradì lórí pápá, nígbà tí wọn y

ÀWỌN AGBÉBỌN PA ÈÈYÀN MẸ́TA NÍ BENUE.Àwọn agbébọn ti pa àwọn èèyàn mẹ́ta  nínú ìkọlù titun tí wọ́n ṣe sí Yelwata ní ìpín...
11/08/2025

ÀWỌN AGBÉBỌN PA ÈÈYÀN MẸ́TA NÍ BENUE.

Àwọn agbébọn ti pa àwọn èèyàn mẹ́ta nínú ìkọlù titun tí wọ́n ṣe sí Yelwata ní ìpínlẹ̀ Benue.
Òwúrọ̀ kùtù òní ni àwọn agbébọn tí wọ́n fura sí pé wọ́n jẹ́ fulani ya wọ inú abúlé náà ní nǹkan bíi aago méje, wọ́n yìnbọn pa àwọn èèyàn mẹ́ta wọ́n sì tún pa àwọn mẹ́ta mìíràn lára.
Lẹ́yìn náà ni wọ́n kó òkú àwọn tí wọ́n pa náà lọ sí àbáwọ ìlú tí wọ́n sì tẹ́ wọn síbẹ̀.
Àwọn ará ìlú tú jáde láti ṣe ìwọ́de tako ìpànìyàn yìí, wọ́n dí ọ̀nà tó lọ sí Abuja láti Makurdi.
Olórí ọ̀dọ́ Yelwata; Achii Mathias ṣe àlàyé pé òwúrọ̀ kùtù ni awọn Fulani náà ya wọ inú abúlé tí wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí ní yìnbọn lákọlákọ.
Gbogbo akitiyan láti kàn sí ilé iṣẹ́ ọlọ́pàá ìpínlẹ̀ Benue kò tíì so èso rere.

ILÉ IṢẸ́ IBOM AIRLINES FI ÒFIN DE COMFORT EMMANSON TÍTÍ LÁÍ.Ilé iṣẹ́ ọkọ̀ òfurufú Ibom Airlines ti fi òfin de arábìnrin ...
11/08/2025

ILÉ IṢẸ́ IBOM AIRLINES FI ÒFIN DE COMFORT EMMANSON TÍTÍ LÁÍ.

Ilé iṣẹ́ ọkọ̀ òfurufú Ibom Airlines ti fi òfin de arábìnrin Comfort Emmanson lẹ́yìn ìtakàngbà tó wáyé láàárín òun àti àwon òṣìṣẹ́ rẹ̀.
Títí ayérayé ni Comfort ò ní le lo ọkọ̀ òfurufú Ibom Air mọ́.
Nínú fọ́nrán tó gbòde kan ni a ti rí àwọn òṣìṣẹ́ IbomAir tí wọ́n ń wọ́ arábìnrin Emmanson bọ́ sílẹ̀ nínú ọkọ̀ bàlúù ní pápákọ̀ òfurufú Muritala Muhammed.
Àlàyé tí ilé iṣẹ́ Ibom Air ṣe ni pé Emmanson gbá etí òṣìṣẹ́ wọn, ó sì tún gbìyànjú àtifọ́ nǹkan mọ́ ọn lórí.
Ṣáájú kí bàlúù náà tó gbéra ní Uyo, wọ́n ní kí Emmanson ó pa ẹ̀rọ ìbánisọ̀rọ̀ rẹ̀ àmọ́ ó kọ̀, awakọ̀ bàlúù náà kéde pé kí gbogbo ènìyàn ó pa ẹ̀rọ ìbánisọ̀rọ̀ wọn, síbẹ̀ Emmanson kọ̀, ẹni tó jókòó sí ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ gba ẹ̀rọ náà lọ́wọ́ rẹ̀ ó sì pa á.
Ọ̀rọ̀ náà dìjà láàrin wọn àmọ́ wọ́n parí ẹ̀.
Nígbà tí wọ́n dé Ikeja ní pápákọ̀ òfurufú Muritala Muhammed, Comfort ṣe ìkọlù sí òṣìṣẹ́ obìnrin tó ní kó pa ẹ̀rọ rẹ̀ ní Uyo, ó mú un láti ẹ̀yìn, ó yọ irun orí rẹ̀, ó gbá etí rẹ̀ ó sì gbìyànjú àtifọ́ panápaná mọ́ ọn lórí.
Awakọ̀ òfurufú ló ké sí àwọn ẹ̀ṣọ́ aláàbò, wọ́k gbìyànjú àti jẹ́ kó sọ̀ kalẹ̀ àmọ́ níṣe ni Emmanson ṣe ìkọlù sí àwọn náà, mi ni wọ́n bá fi agídí tìpǎtìkûkú wọ́ ọ bọ́ sílẹ̀.
Níbi tí wọ́n ti ń wọ́ ọ ni aṣọ rẹ̀ ti ya tí gbogbo ọmú rẹ̀ sì wà ní ìta gedegbe.
Nígbà tí wọ́n tún wọ́ ọ bọ́ sílẹ̀ tán, Emmanson tún mú gbogbo wọn bú ó sì tún gbá ọ̀kan létí.
Ilé iṣẹ́ Ibom Air wí pé àwọn ti fa Comfort Emmanson lé àwọn agbófinró lọ́wọ́ àwọn sì ti kọ ìwé sí àjọ tó ń mójútó ìrìn àjò ojú òfurufú.
Èyí ni àlàyé tí ilé iṣẹ́ Ibom Air ṣe nípa ìṣẹ̀lẹ̀ náà wọ́n sì fi òfin de arábìnrin Emmanson títí ayé, kò tún le lo bàlúù ilé iṣẹ́ wọn mọ́.

Arábìnrin Emmanson ní ìtakàngbà pẹ̀lú àwọn òṣìṣẹ́ IbomAir, wọ́n wọ́ ọ bọ́ sílẹ̀ gbogbo ọmú rẹ̀ ló ti wà lórí ìtàkùn ayél...
11/08/2025

Arábìnrin Emmanson ní ìtakàngbà pẹ̀lú àwọn òṣìṣẹ́ IbomAir, wọ́n wọ́ ọ bọ́ sílẹ̀ gbogbo ọmú rẹ̀ ló ti wà lórí ìtàkùn ayélujára.
Ní báyìí, ó ti wà ní kirikiri yóò sì fi ojú ba ilé-ẹjọ́.

Bí a bá gbé ẹ̀ṣẹ̀ Emmanson sí ẹ̀gbẹ́ ti Wasiu Ayinde, gbọ̀ọ̀rọ̀ gbọọrọ ni ẹ̀ṣẹ̀ Ayinde fi ju ti obìnrín yìí lọ.

Ìbéèrè ni pé kín ni ìdí tí Wasiu Ayinde fi wà ní ilé rẹ̀ tí Emmanson sì wà ní kirikiri?

ÀJỌ EFCC YA BO ILÉ ÌTURA OBASANJO NÍ ABEOKUTA, WỌ́N KỌ́ Ọ̀PỌ̀LỌPỌ̀ ÀWỌN Ọ̀DỌ́KÙNRIN TÍ WỌ́N FURA SÍ PÉ WỌ́N JẸ́ ỌMỌ ‘YÀH...
10/08/2025

ÀJỌ EFCC YA BO ILÉ ÌTURA OBASANJO NÍ ABEOKUTA, WỌ́N KỌ́ Ọ̀PỌ̀LỌPỌ̀ ÀWỌN Ọ̀DỌ́KÙNRIN TÍ WỌ́N FURA SÍ PÉ WỌ́N JẸ́ ỌMỌ ‘YÀHÛ’

Àwọn ọ̀dọ́kùnrin tó lé ní àádọ́rùn-ún ni àwọn òṣìṣẹ́ àjọ tó ń gbógun ti ìwà àjẹbánu EFCC ti kó báyìí ní ilé ìtura Obasanjo tó wà ní Abẹ́òkúta, ìpínlẹ̀ Ogun.
Àwọn ọ̀dọ́ náà kóra jọ fún patí etídò lóru àná ni kó tó di pé àwọn EFCC ya bò wọ́n níbẹ̀.
Ọ̀rọ̀ di bóòlọ-o-yàgò, ìró ìbọn lákọlákọ, wọ́n sì mú àwọn ọ̀dọ́ tó lé ní àádọ́rùn-ún.
Àwọn ọkọ̀ bọ̀gìnnì, ẹ̀rọ ìbánisọ̀rọ̀ olówó iyebíye àti àwọn ohun ìdíyelé mìíràn ni wọ́n gbà lọ́wọ́ wọn.

AKẸ́KỌ̀Ọ́ ILÉ ÌWÉ GÍGA OBAFEMI AWOLOWO DI ÀWÁTÌ, ÀWỌN ALÁṢẸ KÉ GBÀJARÈ.Akẹ́kọ̀ọ́bìnrin ilé ìwé gíga Obafemi Awolowo tó w...
10/08/2025

AKẸ́KỌ̀Ọ́ ILÉ ÌWÉ GÍGA OBAFEMI AWOLOWO DI ÀWÁTÌ, ÀWỌN ALÁṢẸ KÉ GBÀJARÈ.

Akẹ́kọ̀ọ́bìnrin ilé ìwé gíga Obafemi Awolowo tó wà ní Ilé-ifẹ̀ ti di àwátì báyìí, àwọn aláṣẹ ilé ìwé náà ké gbájarè síta.
Dorcas Oseghale ni orúkọ akẹ́kọ̀ọ́ yìí, ẹ̀ka ìmọ̀ kẹ́mísìrì ni ó wà, ó sì ti wà ní ìpele kẹrin.
Ó ti pé ọjọ́ mẹ́rin báyìí tí wọ́n ti fi ojú kan Dorcas gbẹ̀yìn.
Alukoro fún ilé ìwé gíga Obafemi Awolowo; Ọ̀gbẹ́ni Abiodun Olanrewaju ló fi ọ̀rọ̀ yìí léde.
Ó wí pé àwọn àwọn ará ilé Dorcas ni wọ́n fi sùn pé Dorcas kò padà wọlé lẹ́yìn tó lọ ra oúnjẹ.
Ilé Adesanmi tó wà ní ọ̀nà Ìbàdàn ni Dorcas ń gbé pẹ̀lú àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀, lálẹ́ ọjọ́ náà ní nǹkan bíi aago mẹ́jọ alẹ́, Dorcas jáde lọ ra oúnjẹ ní ‘Student’s village’ tó wà ní ọ̀nà Ẹdẹ.
Nígbà tí àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ kò ríi kó dé ni wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí ní pe aago rẹ̀ àmọ́ aago rẹ̀ méjèèjì kò lọ.
Wọ́n fi ọ̀rọ̀ náà tó àwọn ẹ̀ṣọ́ ilé ìwé létí wọ́n sì fi sùn ní àgọ́ ọlọ́pàá.
Ọ̀gá àgbà ilé ìwé gíga Obafemi Awolowo; Ọ̀jọ̀gbọ́n Simeon Bamire ti pàṣẹ fún àwọn ẹ̀ṣọ́ aláàbò ilé ìwé láti sa ipa wọn ó sì tún rọ àwọn ọlọ́pàá láti wá ọmọ náà jáde.

Ipa wo ni Tinubu yóò kó lórí ọ̀rọ̀ Kwam1 àti ValueJet?
09/08/2025

Ipa wo ni Tinubu yóò kó lórí ọ̀rọ̀ Kwam1 àti ValueJet?



Àjọ tó ń mójútó ìgbòkègbodò ọkọ̀ òfurufú ilẹ̀ yìí NCAA ti fi òfin de olórí ọmọ ọba Akile Ìjẹ̀bú tí gbogbo àwọn èèyàn mọ̀ sí Kwam1 fún oṣù mẹ́fà gbáko lórí ohun tó ṣẹlẹ̀ láàrín òun àti àwon òṣìṣẹ́ ValueJet ní pápák....

AUDU OGBEH; ALÁGA ẸGBẸ́ ÒṢÈLÚ PDP TẸ́LẸ̀RÍ TI JÁDE LÁYÉ.Olóyè Audu OGBEH; ẹni tó ti fìgbà kan jẹ́ mínísítà fún ohun ọ̀gb...
09/08/2025

AUDU OGBEH; ALÁGA ẸGBẸ́ ÒṢÈLÚ PDP TẸ́LẸ̀RÍ TI JÁDE LÁYÉ.

Olóyè Audu OGBEH; ẹni tó ti fìgbà kan jẹ́ mínísítà fún ohun ọ̀gbìn ti jáde láyé lẹ́ni ọdún méjìdínlọ́gọ́rin.
Àwọn ẹbí ni wọ́n túfọ̀ ikú Olóyè Audu lónìí, ọjọ́ kẹsàn-án.
Wọ́n wí pé Olóyè Audu dákẹ́ sínú ilé rẹ̀ ní ti àmúwá Ọlọ́run.
Ìwé náà kà báyìí pé ‘ Pẹ̀lú ẹ̀dùn ọkàn ni a fi kéde ikú ọkọ , bàbá àti bàbábàbá wa; Olóyè Audu Ogbeh tó dágbére fáyé lówǔrọ̀ yìí.
Ẹni ọdún méjìdínlọ́gọ́rin ni bàbá wa lásìkò ikú rẹ̀, ipa rere ni bàbá wa fi lélẹ̀ fún àwa ọmọ rẹ̀’
Olóyè Audu ti fìgbà kan jẹ́ alága ẹgbẹ́ òṣèlú PDP nígbà ayé rẹ̀.

DAVIDO ÀTI CHIOMA FI ÀWÒRÁN ÌGBÉYÀWÓ WỌN LÉDE – Ó KỌJÁ BẸ́Ẹ̀.David Adeleke tí gbogbo àwọn èèyàn mọ̀ sí Davido ti fi àwọn...
09/08/2025

DAVIDO ÀTI CHIOMA FI ÀWÒRÁN ÌGBÉYÀWÓ WỌN LÉDE – Ó KỌJÁ BẸ́Ẹ̀.

David Adeleke tí gbogbo àwọn èèyàn mọ̀ sí Davido ti fi àwọn àwòrán ìpalẹ̀mọ́ ìgbéyàwó òun àti aya rẹ̀; Chioma Rowland léde.
Ìgbéyàwó funfun ti ilé ìjọsìn ni èyí tí wọ́n ń mura rẹ̀ báyìí yóò sì wáyé ní Miami, orílẹ̀-èdè Amẹ́ríkà.
Orí ẹ̀rọ ayélujára ti fẹ́rẹ̀ gbiná látàrí àwọn àwòrán náà, inú tọkọtaya ń dùn wọ́n rẹ́rìn-ín músẹ́.

Address

1 Thanes Villa, Seven Sister's Road, Finsbury Park
London
N77PH

Alerts

Be the first to know and let us send you an email when Iwe Iroyin Yoruba posts news and promotions. Your email address will not be used for any other purpose, and you can unsubscribe at any time.

Contact The Business

Send a message to Iwe Iroyin Yoruba:

Share