Iwe Iroyin Yoruba

Iwe Iroyin Yoruba Ẹ káàbọ̀ sí Ìkànnì Ìwé Ìròyìn Yorùbá fún ìgbélárugẹ àwùjọ Yorùbá.Aǹfààní wà láti mọ̀ nípa ilẹ Yòrùbá.

ILÉ ẸJỌ́ KỌ̀ LÁTI FAGÍ LÉ ÌWỌ́DE TÍ YÓÒ WÁYÉ LỌ́JỌ́ AJÉ.Ilé éjọ́ gíga Abuja ti fagi lé ẹjọ́ tí ...
17/10/2025

ILÉ ẸJỌ́ KỌ̀ LÁTI FAGÍ LÉ ÌWỌ́DE TÍ YÓÒ WÁYÉ LỌ́JỌ́ AJÉ.

Ilé éjọ́ gíga Abuja ti fagi lé ẹjọ́ tí ilé iṣẹ́ ọlọ́pàá pè lórí ìwọ́de tí yóò wáyé ní ọjọ́ Ajé, Ogúnjọ́, oṣù Ọ̀wàrà.
Ilé iṣẹ́ ọlọ́pàá bèèrè fún ìfagílé ìwọ́de náà pé yóò da omi àlàáfíà ìlú rú àmọ́ Adájọ Umar pàṣẹ kí ìwọ́de náà ó wáyé.

‼️🗣🗣🗣 ✊ ✊🏿

MAMUDA GÚN ỌLỌ́KADÀ LỌ́BẸ, O TÚN GBÉ Ọ̀KADÀ RẸ̀ LỌ.Ọwọ́ àwọn ọlọ́pàá ìpínlẹ̀ Bauchi ti tẹ ọmọku...
17/10/2025

MAMUDA GÚN ỌLỌ́KADÀ LỌ́BẸ, O TÚN GBÉ Ọ̀KADÀ RẸ̀ LỌ.

Ọwọ́ àwọn ọlọ́pàá ìpínlẹ̀ Bauchi ti tẹ ọmọkùnrin ẹni ọgbọ̀n ọdún kan tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Mamuda Zakari Yau lórí ẹ̀sùn ìpànìyàn àti i-digunjalè.
Àlàyé tí a rí gbà láti ẹnu alukoro fún ilé iṣẹ́ ọlọ́pàá ìpínlẹ̀ náà nip é Mamuda fẹ́ ṣe ìgbéyàwó ó sì nílò owó fún ètò ìgbéyàwó náà. Èyí ló mú un lọ dá Zango Saidawa; ẹni ọdún mẹ́ẹ̀dọ́gbọ̀n lọ́nà, ó gún un lọ́bẹ pa ó sì gbé ọ̀kadà rẹ̀ sá lọ.
Mamuda jẹ́wọ́ pé òun gún Zango lọ́bẹ lóòótọ́ àmọ́ òun kò lérò láti pa á, ó ní òun ṣe èyí láti rí owó fẹ́ ìyàwó kẹta.

🔫 🔫🙏🏾 #newsupdate

ÌYAWÓ DÁKÚ NÍLÉ ẸJỌ́ NÍGBÀ TÍ ỌKỌ RẸ̀ TAKÚ LÓRÍ ÌKỌ̀SÍLẸ̀. Ìyàwó ilé kan ti dákú nílé ẹjó...
17/10/2025

ÌYAWÓ DÁKÚ NÍLÉ ẸJỌ́ NÍGBÀ TÍ ỌKỌ RẸ̀ TAKÚ LÓRÍ ÌKỌ̀SÍLẸ̀.

Ìyàwó ilé kan ti dákú nílé ẹjọ́ nígbà tí ọkọ rẹ̀ takú pé dandan àfi kí ìgbéyàwó náà túká.
Mulikat Yusuf ni orúkọ obìnrin yìí nígbà tí ọkọ rẹ̀ ń jẹ́ Ishaq Abdulganiyu. Agbègbè Igboro ní ìpínlẹ̀ Kwara ni ilé wọn wà.
Ishaq fi àáké kọ́rí nílé ẹjọ́ pé òun kò fẹ́ Mulikat mọ́ kí adájọ́ ó tú ìgbéyàwó náà ká. Ó wí pé ìgbéyàwó náà ti sú òun, ìjà ni ní gbogbo ìgbà òun kò ṣe mọ́.
Tẹkún tẹkún ni Mulikat fi bẹ adájọ́ Toyin Aluko pé òun kò ṣe tán àti kọ ọkọ òun sílẹ̀, ó ní ọmọ mẹ́fà ni òun bí fún un kí adájọ́ ó bá òun bẹ̀ ẹ́.
Nígbà tí ọkọ rẹ̀ kọ̀ jálẹ̀ ni ó múdìí lọlẹ̀ tó sì dákú gbọrangandan. Àwọn èrò ilé ẹjọ́ ṣe aájò rẹ̀, wọ́n rọ́ omi lé e lórí kó tó jí sáyé padà.
Adájọ́ Toyin Aluko rọ Mulikat láti lo gbogbo ọgbọ́n tó bá mọ̀ tó le fi fa ọkọ rẹ̀ mọ́ra padà, ó sún ìgbẹ́jọ́ náà sí ọjọ́ kẹwàá, oṣù Ọ̀pẹ, ọdún 2025.

Ìròyìn tó gbòde
17/10/2025

Ìròyìn tó gbòde



Ìyá kan àti ọmọ rẹ̀ ti gbẹ́mìí mìn lẹ́yìn tí wọ́n jẹ àkàrà òyìnbó ayẹyẹ ọjọ́ ìbí kan ní orílẹ̀-ède Brazil. Ana Maria de Jesus ni orúkọ obìnrin yìí, Castilho ni orúkọ ọmọ rẹ̀. A gbọ́ pé mọ̀lẹ́bí wọ...

17/10/2025
17/10/2025

Ǹjẹ́ ó yẹ kí èèyàn ó fura sí àbúrò rẹ̀?

Ì̀YÁ ÀTI ỌMỌ KÚ LẸ́YÌN TÍ WỌ́N JẸ ÀKÀRÀ ÒYÌNBÓ ỌJỌ́ ÌBÍ.Ìyá kan àti ọmọ rẹ̀ ti gbẹ́mìí mì...
16/10/2025

Ì̀YÁ ÀTI ỌMỌ KÚ LẸ́YÌN TÍ WỌ́N JẸ ÀKÀRÀ ÒYÌNBÓ ỌJỌ́ ÌBÍ.

Ìyá kan àti ọmọ rẹ̀ ti gbẹ́mìí mìn lẹ́yìn tí wọ́n jẹ àkàrà òyìnbó ayẹyẹ ọjọ́ ìbí kan ní orílẹ̀-ède Brazil.
Ana Maria de Jesus ni orúkọ obìnrin yìí, Castilho ni orúkọ ọmọ rẹ̀. A gbọ́ pé mọ̀lẹ́bí wọn kan ṣe ayẹyẹ ọjọ́ ìbí àmọ́ Ana kò ráyè lọ. Ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ náà ni àbúrò Ana tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Patricia mú ègé àkàrà oyìnbó wá fún ẹ̀gbọ́n rẹ̀; Ana ní ilé.
Ana àti àwọn ọmọ́ rẹ̀ méjì; Castilho àti Larissa ni wọ́n jẹ àkàrà òyìnbó náà, kò pẹ́ ni inú bẹ̀rẹ̀ sí run wọ́n tí àárẹ̀ sì mú wọn, ilé ìwòsàn Heliopolis ni wọ́n gbé wọn lọ.
Ana àti Castilho padà kú sílé ìwòsàn àmọ́ Larissa yè. Àyẹ̀wò àwọn dọ́kítà fi hàn pé wọ́n jẹ àwọn kẹ́mikà apakòkòrò tí wọ́n fi ń ṣe ọṣẹ.
Ẹ̀rọ akáwòrán ilé Ana gbé Patricia nígbà tó gbé àkàrà òyìnbó náà wá fún wọn ní èyí tó sọ ọ́ di afurasí. Yàtọ̀ sí fọ́nrán yìí, àyẹ̀wò ẹ̀rọ ìbánisọ̀rọ̀ rẹ̀ ò, wọ́n bá àwọn ìbéèrè tó ti bèèrè lórí GOOGLE bíi ‘ṣé ọṣe le pa èèyàn? Ṣé ìpakòkòrò le pa èèyàn? Ìgbà wò ni ẹni tó bá jẹ ipakòkòrò máa kú? Àti bẹ́ẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ.
Bákan náà ni àyẹ̀wò àpò owó Ana fi hàn pé ó ti tari ọ̀pọ̀ owó sí Patricia àti ọkọ rẹ̀; Leonardo ní èyí tó yá wọn àmọ́ tí kò dá ọ̀kankan padà.
Àwọn ọlọ́pàá fura pé Patricia àti ọkọ rẹ̀ kò fẹ́ dá àwọn owó náà padà ni wọ́n ṣe pa Ana àti ọmọ rẹ̀.

Ọwọ́ Gómìnà Sanwoolu rèé funfun nini
16/10/2025

Ọwọ́ Gómìnà Sanwoolu rèé funfun nini



Ìjọba ìpínlẹ̀ Èkó ti fèsì sí ọjà Festac tí wọ́n wó ní ọ̀sẹ̀ tó kọjá, wọ́n ní ó jẹ́ ohun ìyàlẹ́nu fún àwọn pé àwọn èèyàn kan le dá irú rẹ̀ láṣà. Gómìnà ìpínlẹ̀ Èkó; Babajide Sanwoolu wí pe...

Big thanks to Abdulazeez Zainab, Rasheed Fadairo Adetoye, Sikiru Ayo Adeyemo, Ayoola Idera-Oluwa Fayomi, Jimoh Olamileka...
16/10/2025

Big thanks to Abdulazeez Zainab, Rasheed Fadairo Adetoye, Sikiru Ayo Adeyemo, Ayoola Idera-Oluwa Fayomi, Jimoh Olamilekan Noj, Buhari Muhammed Adetunji, Olori Abiodun Adekola, Adenike Ayinde, Oyelekan Adigun, Prince Raphael Sola Adeyele, Hafeez Adeoye Adewale, Kayode Adetunji, Joshua Olakanmi Oladeji, Alabi Temmytayor, Nasir Adesola Adetokun, Babajide Awodiji, Wasiu Olayinka Abdulrahman, Atunrase Abimbola, Olalekan Akinkunmi Adisa, Arolagbade Waheed Oyeleke, Adekunle Gold, Taofeek Afeez, Ojo Iyiade, Ibrahim Temitope Awoyemi, Adeadun Ayinke, Bola Blacky, Ambali Akanfe Tijani, Ismail Ajibade, Ipadeola Samuel Oluwagbotemi

for all of your support! Congrats for being top fans on a streak 🔥!

Shout out to my newest followers! Excited to have you onboard! Nathaniel Oluwadamilare, Oyeyemi Ganiyu, Mustapha Aliu, I...
16/10/2025

Shout out to my newest followers! Excited to have you onboard! Nathaniel Oluwadamilare, Oyeyemi Ganiyu, Mustapha Aliu, Ibijola Tope Elijah, Musa Adeniyi Adeoye, Kabiru Azeez, Abike Sukurat, Johel Sunday Agbaje, Tiamiyu Adekunle Sarafa Sarafa, Tomilayo Abejide, Arashi Zainab Adewunmi, Rashidat Rabiu, Evanson Dawn Maria

ÌJỌBA ÌPÍNLẸ̀ ÈKÓ SỌ OWORONSHOKI DI AHORO LÓRU MỌ́JÚ.Àwọn ará Oworonshoki fi ẹ̀sùn kan ìjọba ìpínlè...
15/10/2025

ÌJỌBA ÌPÍNLẸ̀ ÈKÓ SỌ OWORONSHOKI DI AHORO LÓRU MỌ́JÚ.

Àwọn ará Oworonshoki fi ẹ̀sùn kan ìjọba ìpínlẹ̀ Èkó pé wọ́n da ilé wọn wó lẹ́yìn tí àwọn ti gba gbogbo ìwé ilẹ̀ lábẹ́ òfin.
Òru ọjọ́ kan nínú oṣù kẹwàá ni wọ́n kó àwọn katakata dé tí wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí ní wó ilé mọ́ àọn èèyàn lórí, èérún bíríkì ló jí ẹlòmíràn lórí ibùsùn rẹ̀.
Alága agbègbè náà; Balogun Jamiu ṣe àlàyé lórí ẹ̀rọ amóhùnmáwòrán pé àwọn ti bẹ̀rẹ̀ sí ní tún àwọn ilé wọn kọ́ lẹ́yìn tí wọ́n fún àwwọn ní ìwé pé kí wọn ó tún àwọn ilé náà kọ́, àfi bí wọ́n ṣe kó katakata dé tí wọ́n sì wó gbogbo ilé lọ.
Obìnrin kan tilẹ̀ ta ilé rẹ̀ tó wà ní Ikorodu láti tún èyí tó wà ní Oworonshoki ṣe, ilé ìwòsàn ló balẹ̀ sí nígbà tí wọ́n wó ilé náà.
Balogun wí pé tó fi dé orí ìwé C of O ni gbogbo àwọn ti gbà, síbẹ̀, wọ́n wó àwọn ilé náà.
Femi Badewa; ẹni tí òun náà jẹ́ olùgbé Oworonshoki náà ṣe àlàyé pé òru ni wọ́n dé tí wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí ní wó ilé mọ́ àwọn èèyàn lórí. Ọlọ́pàá mẹ́rin ni wọ́n kó wá, kò sì sí nọ́ḿbà lára ọkọ̀ wọn. Ó wí pé àwọn ajagungbalẹ̀ ni wọ́n ṣe iṣẹ́ náà.
Obìnrin kan náà ṣe àlàyé pé wọ́n sọ fún àwọn pé kí àwọn ó tún àwọn ilé náà kọ́ sí ti ìgbàlódé, kí àwọn ó kọ́ àwọn ilé náà kó rẹwà pé wọn kò fẹ́ ilé àtijọ́ ní ibẹ̀ mọ́, ìdí nip é Oworonshoki súnmọ́ afárá Third Mainland.
Obìnrin yìí wí pé ìwé ẹ̀rí òun nìkan ni òun rí mú jáde, gbogbo ẹrù rẹ̀ ni wọ́n wó mọ́ ilé.
Ìjọba ìpínlẹ̀ Èkó fèsì láti ẹnu Oluyinka Olumide pé ìjọba kò ní fún àwọn èèyàn náà ní owó gbà-má-bínú nítorí pé wọn kò ní ìwé àṣẹ fún àwọn ilé náà.
Ó wí pé ó ṣe pàtàkì fún àwọn láti wó àwọn ilé náà nítorí pé wọ́n ń dí ṣíṣàn omi lọ́wọ́ ní èyí tó le fa ewu.

À KÒ MỌ̀ NÍPA ỌJÀ FESTAC TÍ WỌ́N WÓ – ÌJỌBA ÌPÍNLẸ̀ ÈKÓ.Ìjọba ìpínlẹ̀ Èkó ti fèsì sí ọjà Fes...
14/10/2025

À KÒ MỌ̀ NÍPA ỌJÀ FESTAC TÍ WỌ́N WÓ – ÌJỌBA ÌPÍNLẸ̀ ÈKÓ.

Ìjọba ìpínlẹ̀ Èkó ti fèsì sí ọjà Festac tí wọ́n wó ní ọ̀sẹ̀ tó kọjá, wọ́n ní ó jẹ́ ohun ìyàlẹ́nu fún àwọn pé àwọn èèyàn kan le dá irú rẹ̀ láṣà. Gómìnà ìpínlẹ̀ Èkó; Babajide Sanwoolu wí pé òun kò mọ̀ nípa bí wó.n ṣe wó ọjà náà.
Mukaila Sanusi; ẹni tó jẹ́ adarí ẹka ọ̀rọ̀ ìlú ní ilé iṣẹ́ ètò ìlú ló bu ọwọ́ lu àtẹ̀jáde náà tí wọ́n gbé jáde lọ́jọ́ ìṣẹ́gun, ọjọ́ kẹrìnlá, oṣù Ọ̀wàrà.
Nínú rẹ̀ la ti kà á pé ohun tí àwọn ń gbọ́ kiri nígboro kò rí bẹ́ẹ̀ o, Gómìnà Babajide Sanwoolu kò mọ nǹkankan nípa bí wọ́n ṣe lọ ó gbogbo ọjà náà kanlẹ̀ kódá, ẹ̀ka ètò ìlú gan-an kò mọ̀ nípa rẹ̀, ó ya àwọn gan-an lẹ́nu nígbà tí wọ́n gbọ́.
Ìjọba ìpínlẹ̀ Èkó kò le ṣàdédé wó dúkìá àwọn èèyàn, gbogbo ohun ló létò lábẹ́ òfin, nítorí ìdí èyí, a kò mọ̀ nípa wíwó ọjà náà – Oluyinka Olumide
Olumide bá àwọn tí wọ́n pàdánù dúkíà wọn kẹ́dùn, ó wí pé ọwọ́ Babajide Sanwoolu rèé funfun.

Address

1 Thanes Villa, Seven Sister's Road, Finsbury Park
London
N77PH

Alerts

Be the first to know and let us send you an email when Iwe Iroyin Yoruba posts news and promotions. Your email address will not be used for any other purpose, and you can unsubscribe at any time.

Contact The Business

Send a message to Iwe Iroyin Yoruba:

Share