Iwe Iroyin Yoruba

Iwe Iroyin Yoruba Ẹ káàbọ̀ sí Ìkànnì Ìwé Ìròyìn Yorùbá fún ìgbélárugẹ àwùjọ Yorùbá.Aǹfààní wà láti mọ̀ nípa ilẹ Yòrùbá.

GÓMÌNÀ SANWOOLU PÀṢẸ KKÍ ÌWÁDÌÍ Ó WÁYÉ LÓRÍ IKÚ ÀWỌN ỌMỌ ÌBEJÌ TÍ WỌ́N KÚ LẸ́YÌN ABẸ́RẸ́ A...
17/01/2026

GÓMÌNÀ SANWOOLU PÀṢẸ KKÍ ÌWÁDÌÍ Ó WÁYÉ LÓRÍ IKÚ ÀWỌN ỌMỌ ÌBEJÌ TÍ WỌ́N KÚ LẸ́YÌN ABẸ́RẸ́ ÀJẸSÁRA.

Gómìnà ìpínlẹ̀ Èkó; Babajide Sanwoolu ti pàṣẹ kí ìwádìí ìjìnlẹ̀ ó wáyé lórí ikú àwọn ọmọ ìbejì tí wọ́n kú lẹ́yìn wákàtí mẹ́rìnlélógún tí wọ́n gba abẹ́rẹ́ àjẹsára.
Gómìnà sọ èyí lẹ́yìn tí bàbá àwọn ọmọ náà fi ẹ̀sùn kan ilé ìwòsàn ìjọba alábọ́dé kan tó wà ní Èkó pé abẹ́rẹ́ àjẹsára wọn ló pa àwọn ọmọ rẹ̀ ìbejì ọkùnrin méjì.
Gómìnà bá Samuel Alozie; bàbá àwọn ọmọ náà kẹ́dùn, ó ní àwọn ti bẹ̀rẹ̀ ìwádìí lórí ikú àwọn ọmọ méjì náà. Ọ̀rọ̀ rẹ̀ lọ báyìí pé wọ́n ti fún ọ̀pọ̀ àwọn ọmọ ní abẹ́rẹ́ àjẹsára tí wọ́n fún àwọn ìbejì náà ṣáájú wọn àti lẹ́yìn tí wọ́n fún wọn tí kò sì sí èyí tó gbòdì lára rẹ̀.
Èsì àyẹ̀wò òkú àwọn ọmọ náà yóò jáde síta lọ́gán tí àyẹ̀wò náà bá parí – ìjọba ìpínlẹ̀ Èkó.

ỌKỌ̀ ÀJÀGBÉ AGBÉPO WÓ LÉ ỌKỌ̀ SUV LÓRÍ NÍ ÌBÀDÀN.Ọkọ̀ àjàgbé agbépo kan tó kún dẹ́nu bámú ti ...
17/01/2026

ỌKỌ̀ ÀJÀGBÉ AGBÉPO WÓ LÉ ỌKỌ̀ SUV LÓRÍ NÍ ÌBÀDÀN.

Ọkọ̀ àjàgbé agbépo kan tó kún dẹ́nu bámú ti gbókìtì ní ojú ọ̀nà márosẹ̀ Akala ní Ibadan. Orí ọkọ̀ ayọ́kẹ́lẹ́ SUV kan tí wọ́n gbé kalẹ̀ ni ó dà wó lé lórí tí ọkọ̀ náà sì parẹ́ mọ́lẹ̀.
Obìnrin ni ẹni tó ni ọkọ̀ yìí, nínú fọ́nrán rẹ̀ tó gbòde ni a ti rí obìnrin yìí tó bu awakọ̀ so pé yóò ra ọkọ rẹ̀ padà lódidi. Ó mú ẹ̀rọ ìbánisọ̀rọ̀ rẹ̀ ó sì ń pe ọkọ rẹ̀.
Kò sí ẹni tó farapa nínú ìṣẹ̀lẹ̀ yìí bẹ́ẹ̀ sì ni ọkọ̀ agbépo náà kò gbaná.

BÀBÁ ÌBEJÌ BÈÈRÈ FÚN ÌWÁDÌÍ LÓRÍ IKÚ ÀWỌN ỌMỌ RẸ̀ LẸ́YÌN TÍ WỌ́N GBA ABẸ́RẸ́ ÀJẸSÁRA.Ọkùn...
17/01/2026

BÀBÁ ÌBEJÌ BÈÈRÈ FÚN ÌWÁDÌÍ LÓRÍ IKÚ ÀWỌN ỌMỌ RẸ̀ LẸ́YÌN TÍ WỌ́N GBA ABẸ́RẸ́ ÀJẸSÁRA.

Ọkùnrin kan tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Samuel Alozie ti ké gbàjarè síta lẹ́yìn tí ó pàdánú àwọn ọmọ rẹ̀ ìbejì ọkùnrin lẹ́yìn wàkátì mẹ́rìnlélógún tí wọ́n gba abẹ́rẹ́ àjẹsára.
Bàbá ìbejì fi ẹ̀sùn kan ilé ìwòsàn ìjọba alábọ́dé kan ní ìpínlẹ̀ Èkó pé òun kó àwọn ọmọ òun, ìbejì ọkùnrin àwọn ọmọ oṣù mẹ́sàn-án lọ gba abẹ́rẹ́ àjẹsára ní ọjọ́ kẹrìnlélógún, oṣù Ọ̀pẹ.
Ó ní àwọn ọmọ náà bẹ̀rẹ̀ sí ní gbóná òun sì fún wọn ní parasitamọ́ọ̀ bí nọ́ọ́sì náà ṣe sọ. Ó fi omi tutu wẹ àwọn ọmọ náà àmọ́ ìgbóná náà kò dínkù bẹ́ẹ̀ sì ni àwọn ọmọ náà kò ní okun nínú mọ́. Ọjọ́ kejì tíí ṣe ọjọ́ ọdún kérésì ni àwọn ọmọ náà kú sílé ìwòsàn.
Alozie ṣe àlàyé pé ilé ìwòsàn náà wí pé oúnjẹ tí òun fún wọn jẹ ló pa àwọn ọmọ náà. Ó ní òun kò gba èyí nítorí pé oúnjẹ náà kò pa wọ́n láti oṣù kan títí oṣù mẹ́sàn-án.
Ọ̀rọ̀ rẹ̀ tẹ̀síwájú pé àwọn ọmọ náà kò ṣe àìsàn láti ìgbà tí òun ti bí wọn, lọ́jọ́ tí wọ́n lọ gba abẹ́rẹ́ náà, koko lara wọn le, ìgbà tí wọ́n gba abẹ́rẹ́ náà tán ni wọn kò le jẹun, sọ̀rọ̀ tàbí ṣeré mọ́.
Àwọn ọmọ náà kò gba abẹ́rẹ́ níbòmíràn láti ìgbà tí ó ti bí wọn, lọ́jọ́ tí wọ́n gba àgbàkẹ́yìn náà, nọ́ọ̀sì titun ló fún wà lẹ́nu iṣẹ́ lọ́jọ́ náà kìí ṣe èyí tí wọ́n mọ̀ tẹ́lẹ̀.
Alozie ra ọwọ́ ẹ̀bẹ̀ sí àwọn agbẹjọ́rò àti ajàfẹ́tọ̀ọ́mọnìyàn pé kí wọn ó dìde ìrànlọ́wọ́ fún òun láti rí ìdájọ́ òdodo lórí ikú àwọn ọmọ náà. Ó ní wọ́n ṣe àyẹ̀wò àwọn ọmọ náà nílé ìwòsàn ìjọba wọ́n sì ní kòkòrò inú oúnjẹ ló pa wọ́n, ó ní òun kò gba èyí gbọ́ nítorí ilé ìwòsàn ìjọba ni wọ́n ti ṣe àyẹ̀wò náà òṣìṣẹ́ ìjọba sì ni ó fún wọn ní abẹ́rẹ́.
Alozie ti sin òkú àwọn ọmọ náà àmọ́ ó ní ẹ̀mí wọn kò sinmi nítorí ikú àìtọ́jọ́ ni wọ́n kú.



#ᴠᴀᴄᴄɪɴᴀᴛɪᴏɴᴅᴏɴᴇ

Big thanks to Abdulazeez Zainab, Hafeez Adeoye Adewale, Rasheed Fadairo Adetoye, Bola Blacky, Autumn White, Sikiru Ayo A...
17/01/2026

Big thanks to Abdulazeez Zainab, Hafeez Adeoye Adewale, Rasheed Fadairo Adetoye, Bola Blacky, Autumn White, Sikiru Ayo Adeyemo, Ayoola Idera-Oluwa Fayomi, Zi Zi, Jimoh Olamilekan Noj, Buhari Muhammed Adetunji, Olori Abiodun Adekola, Adenike Ayinde, Oyelekan Adigun, Prince Raphael Sola Adeyele, Kayode Adetunji, Joshua Olakanmi Oladeji, Alabi Temmytayor, Sulaimon Lateef, Nasir Adesola Adetokun, Babajide Awodiji, Atunrase Abimbola, Olalekan Akinkunmi Adisa, Arolagbade Waheed Oyeleke, Adekunle Gold, Taofeek Afeez, Ojo Iyiade, Ibrahim Temitope Awoyemi, Adeadun Ayinke, Ambali Akanfe Tijani, Ismail Ajibade, Ipadeola Samuel Oluwagbotemi

for all of your support! Congrats for being top fans on a streak 🔥!

Big shout out to my newest top fans! 💎 Abdulazeez Zainab, Hafeez Adeoye Adewale, Rasheed Fadairo Adetoye, Bola Blacky, A...
17/01/2026

Big shout out to my newest top fans! 💎 Abdulazeez Zainab, Hafeez Adeoye Adewale, Rasheed Fadairo Adetoye, Bola Blacky, Autumn White, Sikiru Ayo Adeyemo, Ayoola Idera-Oluwa Fayomi, Zi Zi, Jimoh Olamilekan Noj, Buhari Muhammed Adetunji, Olori Abiodun Adekola, Adenike Ayinde, Oyelekan Adigun, Prince Raphael Sola Adeyele, Kayode Adetunji, Joshua Olakanmi Oladeji, Alabi Temmytayor, Sulaimon Lateef, Nasir Adesola Adetokun, Babajide Awodiji, Atunrase Abimbola, Olalekan Akinkunmi Adisa, Arolagbade Waheed Oyeleke, Adekunle Gold, Taofeek Afeez, Idowu Olayiwola, Ojo Iyiade, Ibrahim Temitope Awoyemi, Adeadun Ayinke, Ambali Akanfe Tijani, Ismail Ajibade, Ipadeola Samuel Oluwagbotemi

Drop a comment to welcome them to our community, fans

Shout out to my newest followers! Excited to have you onboard! Ayinla Ibrahim, Telèjayé Francis A. Káyòdé, Olanrewaju Re...
17/01/2026

Shout out to my newest followers! Excited to have you onboard! Ayinla Ibrahim, Telèjayé Francis A. Káyòdé, Olanrewaju Remilekun, Akinfemi Akintunde, Busayo Oyebisi, Ayodele Mogaji, Alelagba Opeyemi, Baylo Atanda, Ejiwunmi Ejireoyila EdunjobiOba Omo, Olayinka Toyin, Mujeeb Jamiu, Janet Folasade, Funke Pearl, Daniel Kuye, Eyiowuawi Ramotalahi Adebisi, Shuib Ishola, Oyekanmi Olalekan, Adesikemi Taiwo, Inaolaji Marruff Abidoye, Imam Mustapha Abubakar Olayiwola, الأستاذ الشيخ المركزي

ÌJỌBA ÌPÍNLẸ̀ KANO TI PÀṢẸ KÍ ÌWÁDÌÍ Ó WÁYÉ LÓRÍ IKÚ AISHATU UMAR.Ìjọba ìpínlẹ̀ Kano ti pàṣẹ ...
16/01/2026

ÌJỌBA ÌPÍNLẸ̀ KANO TI PÀṢẸ KÍ ÌWÁDÌÍ Ó WÁYÉ LÓRÍ IKÚ AISHATU UMAR.

Ìjọba ìpínlẹ̀ Kano ti pàṣẹ kí ìwádìí ó wáyé lórí ikú tó pa ìyàwó ilé kan tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Aishatu Umar lẹ́yìn tí wọ́ fi ẹ̀sùn ikú rẹ̀ kan ilé ìwòsàn Abubakar Umar Urology tó wà ní ìpínlẹ̀ náà.
Ìjọba ìpínlẹ̀ Kano sọ èyí di mímọ̀ láti ẹnu agbẹnusọ wọn; Samira Suleiman, nínú rẹ̀ ni wọ́n ti kọ ó pé àwọn bá ẹbí Aishatu Umar kẹ́dùn, ìwádìí ìjìnlẹ̀ yóò wáyé lórí ìṣẹ̀lẹ̀ náà, ilé ìwòsàn Abubakar Umar yóò ṣe àlàyé bí ọ̀rọ̀ náà ṣe jẹ́.
Ọ̀rọ̀ náà tẹ̀síwájú pé àwọn kò ní fi igbá kan bọ̀kan nínú nínú ìwádìì náà. Ẹ̀mí àwọn èèyàn ṣe pàtàkì, àwọn yóò ríi dájú pé ilé ìwòsàn náà fi ojú winá òfin bí wọ́n bá fi le jẹ̀bi ẹ̀sùn náà.
Èyí jẹyọ lẹ́yìn tí àwọn ẹbí Aishatu Umar fi ẹ̀sùn kan ilé ìwòsàn náà pé wọ́n dágúlá nígbà tí wọ́n ń ṣe iṣẹ́ abẹ fún obìnrin náà. Èyí mú kí inú bẹ̀rẹ̀ sí ní run ún tí ó sì ń padà lọ sí ilé ìwòsàn náà.
Òògùn inú rírun ni wọ́n ń fún un fún odidi oṣù mẹ́rin láìṣe àyẹ̀wò ohun tó ṣe okùnfà inú rírun náà. Lẹ́yìn oṣù mẹ́rin ni wọ́n tó ṣe àyẹ̀wò fínní inú rẹ̀ tí wọ́n sì bá àlùmọ́gàjí nínú rẹ̀. èyí já sí pé wọ́n gbàgbé àlùmọ́gàjí sínú obìnrin náà nígbà tí wọ́n ṣiṣẹ́ abẹ náà lóṣù mẹ́rìn sẹ́yìn. Wọ́n dájọ́ iṣẹ́ abẹ mìíràn tí wọn yóò fi yọ ọ́ àmọ́ Aishatu kú kó tó di ọjọ́ náà.
Àwọn ẹbí rẹ̀ fi ẹ̀sùn kan ilé ìwòsàn Abubakar Umar Urology pé wọ́n kò ṣe iṣẹ́ wọn bíi iṣẹ́ wọ́n sì fi àiàbìkítà wọn pa Aishatu. Ọmọ márùn-ún ni Aishatu fi sílẹ̀ sáyé lọ.

WỌ́N DÁNÁ SUN AFURASÍ OLÈ KAN NÍ ÌPÍNLE BENUE.Àwọn èrò tí inú bí ti dáná sun afurasí olè kan ní àdo...
16/01/2026

WỌ́N DÁNÁ SUN AFURASÍ OLÈ KAN NÍ ÌPÍNLE BENUE.

Àwọn èrò tí inú bí ti dáná sun afurasí olè kan ní àdojúkọ ilé epo Prime ní Makurdi tíí ṣe olú ìlú ìpínlẹ̀ Benue.
A gbọ́ pé afurasí náà já ọ̀kadà náà gbà lọ́wọ́ ọlọ́kadà kan ní òpópónà Ahamdu Commisi, àwọn ọlọ́kadà yòókù tí wọ́n ríi lé e títí wọ́n sì báa ní ilé epo Prime nígbà tó fẹ́ gbé ọ̀kadà náà sọdá.
Wọn kò tilẹ̀ dúró de àwọn ọlọ́pàá, wọ́n wọ inú ìsọ̀ fọga kan tó wà nítosì, wọ́n kó àwọ àlokù táyà jọ wọ́n sì dáná sun ún lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀.
Ẹni tó ni ọ̀kadà náà ṣe àlàyé pé òun ń gùn ún bọ̀ ni afurasí náà dá òun dúró bíi èrò, ó yọ ìbọn sí òun ó sì ní kí òun ó bọ́ sílẹ̀. Bí ó ṣe ń gbé ọ̀kadà náà lọ ni òun bẹ̀rẹ̀ sí ní kigbe olè tí àwọn ará yòókù rẹ̀ fi gbá tẹ̀lé e.
Ó ní mílíọ́nù méjì náírà ni òun ṣẹ̀ṣẹ̀ fi ra ọ̀kadà náà.

🏃🏽⛏⚒🔨🗡⚔️🔪⚰️

AWAKỌ̀ BRT GBÁ ÈÈYÀN KAN PA LÓJÚ Ọ̀NÀ IKEJA.Ìjọba ti mú awakọ̀ ìjọba BRT kan sí àhámọ́ lórí ẹ̀sùn...
16/01/2026

AWAKỌ̀ BRT GBÁ ÈÈYÀN KAN PA LÓJÚ Ọ̀NÀ IKEJA.

Ìjọba ti mú awakọ̀ ìjọba BRT kan sí àhámọ́ lórí ẹ̀sùn pé ó gbá ẹnìkan tí ẹni náà sì kú.
Àlàyé tí a rí gbà láti ọ̀dọ LAMATA ni pé arábìnrin náà tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Elizabeth Fresh fẹ́ sọdá títì ní ojú ọ̀nà Ikeja ní àbáwọ pápákọ̀ òfurufú ni ọkọ̀ BRT náà gbá a tó si kú lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀.
Ọjọ́ kẹsàn-án, oṣù Ṣẹẹrẹ ni ìṣẹ̀lẹ̀ náà ṣẹ̀. Kíá ni awakọ̀ BRT náà ti fi ẹsẹ̀ fẹ́ ẹ àmọ́ ilé iṣẹ́ náà wá a jáde wọ́n sì fà á lé àwọn ọlọ́pàá lọ́wọ́ lọ́jọ́ náà gan-an.
Ilé iṣẹ́ LAMATA bá àwọn ẹbí Fresh kẹ́dùn lórí ìṣẹ̀lẹ̀ náà, wọ́n rọ àwọn èèyàn láti máa ṣe àmúlò afárá ẹlẹ́sẹ̀.

WỌ́N TI DÁ ÒṢÌṢẸ́FẸ̀YÌNYÌ Ẹ̀ṢỌ́ AṢỌ́BODÈ ILẸ̀ WA SÍLẸ̀ LẸ́YÌN OWÓ ÌTÚSÍLẸ̀.Àwọn ajínigbé t...
15/01/2026

WỌ́N TI DÁ ÒṢÌṢẸ́FẸ̀YÌNYÌ Ẹ̀ṢỌ́ AṢỌ́BODÈ ILẸ̀ WA SÍLẸ̀ LẸ́YÌN OWÓ ÌTÚSÍLẸ̀.

Àwọn ajínigbé ti dá Emmanuel Owolabi sílẹ̀ lẹ́yìn tí àwọn ẹbí rẹ̀ san ẹgbẹ̀lẹ́gbẹ̀ mílíọ́nù owó ìtúsilẹ̀ rẹ̀.
Inú ogbó Oro Ago ní ìpínlẹ̀ Kwara ni wọ́n ní àwọn ẹbí rẹ̀ ó ti lọ pàdé rẹ̀ lẹ́yìn tí wọ́n san owó ìtúsílẹ̀ rẹ̀, wọ́n dé inú igbó náà wọ́n sì ríi lóòótọ́ tó ń gbìyànjú àtirìn jágboro.
Ọjọ́ kẹẹ̀dógún, oṣù Ọ̀pẹ ni wọ́n lọ gbé Owolabi ní iwájú ilé rẹ̀, òun nìkan ni wọ́n gbé lọ́jọ́ náà àmọ́ wọ́n yìnbọn pa olóyè kan tó pàdé wọn lọ́nà.
Ìròyìn bí wọ́n ṣe jí Owolabi gbé:
Àwọn agbébọn ya wọ́ Ora ní ibodè ìpínlẹ̀ Ọ̀ṣun àti ìpínlẹ̀ Kwara wọ́n sì gbé bàbá kan tó jẹ́ òṣìṣẹ́fẹ̀yìnyì ní ẹ̀ka aṣọ́bode lọ.
A gbọ́ pé ilé ọ̀gbẹ́ni Emmanuel Owolabi gan-an ni wọ́n ti kó o ní pápá mọ́ra tí wọ́n sì gbé e wọ igbó lọ.
Ìyàwó Emmanuel tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Titilayọ ṣe àlàyé pé ní ọjọ́ Ajé, ìyẹn ọjọ́ kẹẹdógún, oṣù Ọ̀pẹ ni ọkọ òun wá bá òun ní ìsọ̀, ó ní kí òun máa lọ sí ilé lọ dáná pé òun ṣì ń jáde lọ nítòun.
Titilayo ti ìsọ̀ ní aago mẹ́fà àbọ̀ ìrọ̀lẹ́ ó sì lọ ilé láti dáná oúnjẹ alẹ́. Nígbà tó di aago méje ni àwọn agbébọn ya wọ ìlú, ilé rẹ̀ gan-an ni wọ́n mórí lé tààrà. Àlàyé rẹ̀ tẹ̀síwájú pé òun kò kọbi ara sí ìró ìbọn náà nítorí àwọn ọdẹ a máa wọ ìlú wá àmọ́ nígbà tó ń ró lemọ́lemọ́, òun bọ́ sínú àgbàlá láti wo ohun tó ń ṣẹlẹ̀, ó rí àwọn agbébọn náà tí wọ́n fo ìgànná wọlé, ó sọ ède Hausa sí wọn àmọ́ wọ́n lù ú lálùbami wọ́n sì ń bèèrè owó. Ẹ̀kannáà ló gbọ́ ìró ọ̀kadà láti ìta tí wọ́n gbé ọkọ rẹ̀ lọ. Titilayọ̀ rawọ́ ẹ̀bẹ̀ pé kí wọn ó dákun gba ọkọ rẹ̀ kalẹ̀.
Nínú ìkọlù yìí ni àwọn agbébọn náà ti yìnbọn pa olóyè ìlú nígbà tó ń bọ̀ láti oko. Olóyè Dennis ń ti oko bọ̀ ló pàdé àwọn agbébọn yìí, ó fẹ́ sá ni wọ́n bá ta á níbọn tó sì kú.
Ilé iṣẹ́ ọlọ́pàá ìpínlẹ̀ Ọ̀ṣun fi ìdí ìṣẹ̀lẹ̀ náà múlẹ̀ láti ẹnu agbẹnusọ wọn; Abiodun Ojelabi.
Ojelabi ní lọ́gán tí ìṣẹ̀lẹ̀ náà ṣẹ̀ ni àwọn ti kán lu ìgbẹ́ láti gba ọkùnrin náà kalẹ̀, ó ní àwọn ń ṣiṣẹ́ kárakára láti ríi pé Emmanuel padà wálé. Bákan náà ló wí pé ibi tí wọ́n pa olóyè Dennis sí ti kọjá ìpínlẹ̀ Ọ̀ṣun, ìpínlẹ̀ Kwara ni yóò ṣe ìwádìí ikú rẹ̀.
Ní báyìí, Owolabi ti padà dé o, àwọn ẹbí rẹ̀ yọ ayọ̀ pé orí kó o yọ.

# #

Ìròyìn tó gbòde
15/01/2026

Ìròyìn tó gbòde



Òǹkọrin ẹ̀mí nnì; Bukunmi Akinaanu tí gbogbo àwọn èèyàn mọ̀ sí omijé ojú mi ti dágbére fáyé lọ́jọ́ ìṣẹ́gun, ọjọ́ kejìlá, oṣù Ṣẹẹrẹ. Ilé ìwòsàn kan ní ìpínlẹ̀ Èkó ni ó dákẹ́ sí. Ọ̀rẹ́ rè....

Address

1 Thanes Villa, Seven Sister's Road, Finsbury Park
London
N77PH

Alerts

Be the first to know and let us send you an email when Iwe Iroyin Yoruba posts news and promotions. Your email address will not be used for any other purpose, and you can unsubscribe at any time.

Contact The Business

Send a message to Iwe Iroyin Yoruba:

Share