ALAWIYE Blog

ALAWIYE Blog A ki yin kaabo s'ori a'pere ti o n gbaruku ti idagbasoke Asa ati Ise ede Yoruba. Alawiyeblog !!!

Kínní ẹ̀yin mọ Radio sí ní Yorùbá.Rédíò àbí Ẹ̀rọ asọ̀rọ̀mágbèsì.Ọ̀kan jẹ́ ọ̀rọ̀ àyálòỌ̀kan jẹ́ ọ̀rọ̀ ìpèrí
27/07/2025

Kínní ẹ̀yin mọ Radio sí ní Yorùbá.

Rédíò àbí Ẹ̀rọ asọ̀rọ̀mágbèsì.

Ọ̀kan jẹ́ ọ̀rọ̀ àyálò
Ọ̀kan jẹ́ ọ̀rọ̀ ìpèrí

Ọdúnladé Adékọ́lá pàdánù bàbá rẹ̀ lónìí. Ẹ darapọ̀ mọ́wa láti kíi kú ìdèlé bàbá rẹ̀.
26/07/2025

Ọdúnladé Adékọ́lá pàdánù bàbá rẹ̀ lónìí. Ẹ darapọ̀ mọ́wa láti kíi kú ìdèlé bàbá rẹ̀.

Ṣé ẹ̀yin lè gbà láti fẹ́ẹ?
26/07/2025

Ṣé ẹ̀yin lè gbà láti fẹ́ẹ?

25/07/2025

Lori eto yi, arakunrin Victor Oyejide, Oludari ni ilese Recycledge so nipa bi a se le so Egbin di oro (Waste to Wealth).

Ki ni eyin nse si awon idoti yin ???

Ṣé Yorùbá ní irúfẹ́ èso yìí. Tó bá jẹ́ pé, bẹ́ẹ̀ni, KÍNNÍ ORÚKỌ RẸ̀?
24/07/2025

Ṣé Yorùbá ní irúfẹ́ èso yìí. Tó bá jẹ́ pé, bẹ́ẹ̀ni, KÍNNÍ ORÚKỌ RẸ̀?

AlákọríỌgbọ́n tí mo ní,Kòsí baba ẹni toníi.Ìmọ̀ tí mo mọ̀,Kòsí baba ẹni tómọ̀ọ́.Ilé tí mo kọ,Kò sí ẹnì tó kọ́ rúẹ̀.Aya t...
23/07/2025

Alákọrí

Ọgbọ́n tí mo ní,
Kòsí baba ẹni toníi.
Ìmọ̀ tí mo mọ̀,
Kòsí baba ẹni tómọ̀ọ́.

Ilé tí mo kọ,
Kò sí ẹnì tó kọ́ rúẹ̀.
Aya ti mo fẹ́,
Kòsí sí aya ẹni tó rẹwà to o.

Ọ̀rọ̀ alákọrí lẹgbọ́yẹn,
Ẹni bá dé òpin ìmọ̀,
Ló le sọ pé kò sí ẹnì tó ju òun,
Bẹ́ẹ̀, òpin ìmọ̀ kan ò sí.
Àìmọ̀kanmọ̀kàn ní í rán alákọrí sọ́run.

Bàbá ẹni kan kòní ìrù ẹṣin,
Baba ẹni kan kòní ìrù esin.
Ohun tí a ní lamọ̀,
A kò mọ ohun tá ò ní,
Bóyá ó ju tẹni lọ tàbí rárá.

©Mojuba2025

ÀKỌTỌ́Ṣé ẹ̀yin máa ń ṣe àṣìṣe nígbà tí ẹ bá fẹ́ lo ọ̀rọ̀ yìí  "NÍGBÀ TÍ"Follow Alawiye blog.
22/07/2025

ÀKỌTỌ́

Ṣé ẹ̀yin máa ń ṣe àṣìṣe nígbà tí ẹ bá fẹ́ lo ọ̀rọ̀ yìí "NÍGBÀ TÍ"

Follow Alawiye blog.

21/07/2025

Ajàfẹ́tọmọnìyàn àti Ẹni tí ó ti fi ìgbàkanrí díje fún Ipò Ààrẹ Orílẹ̀-Èdè Nàìjíríà, Omoyele Sòwòrẹ́ fí ẹ̀sùn Kan Ọlọpa kan pé Ó jí ìgò ojú rẹ̀ tí ó pè ní "AL RAYBAN GLASSES" ní òwúrọ́ òní níbi tí Wọ́n tí ń fẹ̀hónúhàn ni Olú ìlúu orílẹ̀-èdè wa, Abuja.

Nje eyin lero pe ọlọ́pàá orílẹ̀ èdè Nàìjíríà le hùwà yìí?

Video credit : Odita Sunday

Ibere ose yi ??
20/07/2025

Ibere ose yi ??

ASÚRÉTETE KÒNÍ KỌJÁ ILÉ, ARÌNGBẸ̀DẸ̀ KAN NÁÀ KÒ NÍ SÙN SỌ́NÀ.MÁ WÒ AGO ALÁAGO SÁRÉ.
19/07/2025

ASÚRÉTETE KÒNÍ KỌJÁ ILÉ, ARÌNGBẸ̀DẸ̀ KAN NÁÀ KÒ NÍ SÙN SỌ́NÀ.

MÁ WÒ AGO ALÁAGO SÁRÉ.

Ẹ BÁ WÀ DÁSI
18/07/2025

Ẹ BÁ WÀ DÁSI

Ẹniìtàn-Awẹ́ kìíníTólání wá ní ẹ̀yín àgbàlá ilé rẹ̀, ó ti ronú gbàgbé ara rẹ̀ sí orí àpòtí tí ó jókòó lé. Ó ń dá rónú " ...
17/07/2025

Ẹniìtàn-Awẹ́ kìíní

Tólání wá ní ẹ̀yín àgbàlá ilé rẹ̀, ó ti ronú gbàgbé ara rẹ̀ sí orí àpòtí tí ó jókòó lé. Ó ń dá rónú " orí Ọ̀kẹ́rẹ́ koko láwo, bàa wí fún ọmọ ẹni a gbọ́. Ìbáwí níí síwájú ìparun. Hmm… a kò kúkú ní wí fún ọmọdé pé kí ó má dẹ́tẹ́ níwọ̀n ìgbà tí ó bá ti le dá igbó gbé" irú ayé ti àìgbọràn máa ń mú ní gbé kò rọrùn, ayé alààyè ni èèyàn máa ń gbé ní ọ̀pọ́ ìgbà, àfi bí ẹni sìn Wọ́n wáyé. Bí ènìyàn kò bá sì gbé irú ìgbé ayé baun, a jẹ pé ìgbẹ́ kiun yóò di kòlọmọ́ sétí àwo gbẹ̀gìrì ayé ẹni. Àbí irú ayé wo wàá lèyìí, láti ọdún mẹ́ẹ̀dọ́gbọ̀n kí ènìyàn sì wá máa ko àjọ́ àìgbọràn, kí ènìyàn sì máa wò egbò tí àìgbọ̀ràn fí sí ojú orúkún ẹni. Èyí gan-an kọjá egbò àdákòjiná. ".... Ó bú sẹkún gbaragada.

Àròkàn tí Tólání ń rò yìí kò jẹ́ kómọ̀ pé ẹnìkan dúró lẹ́yìn òun. Ẹniìtàn dúró tiiri sẹ́yìn Tólání, ó ń wòó tìkàtẹ́gbin, ó pòse sàràsà. Tólání sì wà lórí Àròkàn rẹ̀, ṣe bí ẹni tó bá wo ojú ìyàwó ní yóò mọ̀ bóyá ìyàwó ń sunkún. Tólání kò mọ́ bóyá ẹnìkankan wà lẹ́yìn òun, kò tilẹ̀ mọ̀ bóyá ẹnìkan pòsé sàràsà. Ó tún ronú síta pé " báwo wá ni mo ṣe lè rí májélé náà, ọ̀nà wo ni mo le gbà?"

Àyà ẹniìtàn já pàtì bí rọ́bà fáànù ọkọ̀ tó já ṣùgbọ́n ìkórìíra àti ọgbẹ́ ọkàn tí fọ́ ojú àánú rẹ̀. Ó fọhùn, Ó ní "ẹ fẹ́ gbé májèlé jẹ́ àbí kíni mo gbọ́……… Ọ̀rọ̀ rẹ̀ bá Tólání lójijì nítorí kò mọ̀ pé ẹnìkankan wà ní ẹ̀yìn òun. Kí ẹniìtàn tó sọ̀rọ̀ jálẹ̀ ni Tólání ti ṣubú lulẹ̀ yakata tí ó sì dákú lọ gbọnrangandan. Ẹniìtàn ń sọ̀rọ̀ pẹ̀lú ìbínú," síọ̀, ẹ jẹ́ dìdè nílẹ̀, bí ẹ bá fẹ́ kú, kò sí ẹni tó ní kí ẹ mọ́ gbọ̀runlọ, àwọn tí kò tó yín tí kú, àwọn tó jùyín tí dẹni ànà, pàápàá jùlọ, àwọn tí Wọ́n gbé ayé tó ní ìtumọ̀, tí wọn kò fí ìgbésí ayé wọn ní ọmọ wọn lára, àwọn lamọ̀ pé wọn wáyé, wọn gbé ayé, wọn sì kú ikú tó ní ìtumọ̀, ẹ̀yìn wọn dára torí ilé ọkọ orí wọn ni Wọ́n sìn Wọ́n sí, wọn kò dálémosú sí ilé bàbá wọn kí Wọ́n má tilẹ̀ gbé ilé ọkọ wọn ní òwúrọ̀ kan di alẹ́ rí bíi ti yín yìí. Ẹ jẹ́ dìde, àbí ẹ kò ní dìde. Ẹ sọ ohun tí èmi fẹ́ mọ̀ fún mi ná kí ẹ tó gbọ̀runlọ, ẹ má sọ mí ṣókùnkùn ayérayé. Ẹ jẹ́ kí ayé tèmi náà kóní ojútùú. Àbàwọ́n burúkú ni ìyàn ogún ọdún tí ẹ gbé pamọ́ tí dá sí ayé mi. Gbogbo ọwọ́ mi ni ó ti bó fáláfàla torí bíi ó ṣe gbóná tó. Àná yín korò bíi jogbo, ìgbésí ayé yín dà bí ìsápá. Sebí àwọn àgbà tilẹ̀ sọ pé, ìka tí ó bá sẹ̀ ni ọba máa ń gé? Èwo ni tèmi nínú gbogbo ọ̀ràn yìí? Àbí kí ẹ kúkú má wàá bí mi gan án kò sàn jú hílàhílo tí ẹ kò bá mi yìí lọ? Elédùmarè, dàkún wáá gbà mí ó "

Ẹni ìtàn ríi pé Tólání kò mira rárá, ó sún mọ́ Tólání, ó fàá ní ọwọ́ sókè níbi tí ó ṣubú sí yakata, ọwọ́ Tolani yọ̀ bọ́ pọ́rọ́ ní ọwọ́ rẹ̀. Ẹniìtàn pariwo " háà, mo gbé! Èèmọ̀, èmi kọ́ ni mo pá Wọ́n ó, àbí ṣe Wọ́n tí jẹ májélé tí Wọ́n dárúkọ lẹ́ẹ̀kan ni?"

Ẹ kú ojúlọ́nà

Address

Apata Ibadan

Alerts

Be the first to know and let us send you an email when ALAWIYE Blog posts news and promotions. Your email address will not be used for any other purpose, and you can unsubscribe at any time.

Share