ALAWIYE Blog

ALAWIYE Blog A ki yin kaabo s'ori a'pere ti o n gbaruku ti idagbasoke Asa ati Ise ede Yoruba. Alawiyeblog !!!

TA LÓ RÁNTÍ IKÚ TÓ PA ÌYÁ FẸLÁ ANÍKÚLÁPÓ? Ní ọjọ́ kẹjọ, oṣù kejì ọdún 1977, lẹ́yìn ayẹyẹ kan tí Wọ́n ń pè ní FESTAC '77,...
16/10/2025

TA LÓ RÁNTÍ IKÚ TÓ PA ÌYÁ FẸLÁ ANÍKÚLÁPÓ?

Ní ọjọ́ kẹjọ, oṣù kejì ọdún 1977, lẹ́yìn ayẹyẹ kan tí Wọ́n ń pè ní FESTAC '77, Àwọn kan lára ọmọ ológun orile-ede Naijiria dáná sún Kalakuta Republic tí ọkàn lára èèkàn ìlú àti Ajàfẹ́tọmọnìyàn, Fẹlá Aníkúlápó Ransome Kútì kọ́, Kalakuta Republic yìí wà ní Nọ́mbà 14 Agege, ìdí oro Mushin ní ìpínlẹ̀ èkó.

Gégé bí ÌRÒYÌN tó jáde, Fẹlá Aníkúlápó àti àwọn kan ló fẹ́ pawọ́pọ̀ ṣe ayẹyẹ yìí ṣùgbọ́n àríyànjiyàn kan bẹ́ sílẹ̀ láàrin wọn, Fẹlá Aníkúlápó sọ pé òun kò ní fẹ́ láti pawọ́pọ̀ ṣe ayẹyẹ náà pẹ̀lú wọn mọ́, ó sì lọ dá ṣe ayẹyẹ rẹ̀ lọ́tọ̀. Ìkéde yìí ní Fẹlá ṣe ní oṣù keje ọdún 1976.

Ṣùgbọ́n nígbà tí ó di oṣù kejì ọdún 1977, ó ṣe ayẹyẹ rẹ̀ lẹ́yìn tí ó ti kéde pé òun kò ṣe àjọsepọ̀ pẹ̀lú àwọn tí wọn jọ fẹ́ pawọ́pọ̀ ṣe FESTAC 77 mọ́, ṣùgbọ́n ogunlọ́gọ̀ àwọn tí ó máa ń lọ sí FESTAC 77 tẹ́lẹ̀ ni ó lọ sí ayẹyẹ Fẹlá Aníkúlápó.

Lẹ́yìn èyí, ọ̀gọ̀rọ̀ àwọn ọmọ ológun ni ó wá dáná sun ilé rẹ̀. Ní àsìkò yìí, wọn bá ìyá Fẹlá Aníkúlápó nílé, orúkọ ẹni tíì ṣe Funmilayo Ransome Kuti.

Ọ̀kan láàrin àwọn ọmọ ológun gbé ìyá Fẹlá Aníkúlápó, ó sì ju láti òkè ilé alájà méjì sílẹ̀.

Ràbàràbà yìí ni ìyá Fẹlá Aníkúlápó bá kú. Títí di òní, kò sì ẹni tí ó mọ àwọn tí ó lọ́wọ́ nínú Ìsẹ̀lẹ̀ ibi yìí

Ǹjẹ́ a rí ẹni tí ó rántí?

KI ni 150 ni yoruba?
15/10/2025

KI ni 150 ni yoruba?

ÌṢẸ̀LẸ̀ WÒ NÍ Ó ṢẸLẸ̀ NÍBÀDÀN TÍ Ẹ̀YIN O LE GBÀGBÉ?Ọ̀kan lára ìṣẹ̀lẹ̀ tí èmi kò le gbàgbé ni ọdún tí wọn dìtẹ̀ mọ́ gómìn...
14/10/2025

ÌṢẸ̀LẸ̀ WÒ NÍ Ó ṢẸLẸ̀ NÍBÀDÀN TÍ Ẹ̀YIN O LE GBÀGBÉ?

Ọ̀kan lára ìṣẹ̀lẹ̀ tí èmi kò le gbàgbé ni ọdún tí wọn dìtẹ̀ mọ́ gómìnà Ládọ̀jà gẹ́gẹ́ bí I gómìnà tí Wọ́n sì yọ́ ọ́ nípò fún bí ọdún kan.

Ta ló ti rí irú ìgbín yí I rí?
13/10/2025

Ta ló ti rí irú ìgbín yí I rí?

Ta ló mọ orúkọ Òṣèré tíátà yìí?
12/10/2025

Ta ló mọ orúkọ Òṣèré tíátà yìí?

owe wo?
11/10/2025

owe wo?

Lo Álífàbẹ̀tì Yorùbá láti A títí dé Y dárúkọ àwọn àgbègbè tí ó mọ̀ ní Ìbàdàn
11/10/2025

Lo Álífàbẹ̀tì Yorùbá láti A títí dé Y dárúkọ àwọn àgbègbè tí ó mọ̀ ní Ìbàdàn

Kí Ni 1000 Ní Yorùbá?
11/10/2025

Kí Ni 1000 Ní Yorùbá?

10/10/2025

ÀWỌN MÉJÌ TÍ Ó TẸ̀LÉ OLÚBÀDÀN ṢÙGBỌ́N TÍ KÒ JOYÈ OLÚBÀDÀN

Àwọn méjì tí wọ́n papòdà kí àsìkò ìwúyè wọn tó pé láàrin ọ̀sẹ̀ méjì síra wọn.

Ẹni àkọ́kọ́ ni olóyè Suleman Adegboyega Omiyale, Balogun ilẹ̀ Ìbàdàn, òun ni ó kan gun sí Olúbàdàn tí kò bá sì jọba ní kété tí Olúbàdàn bá wàjà. Ṣùgbọ́n, ní ọjọ́ keje oṣù kọkànlá ọdún 2015 ni ó papòdà ní ẹni ọdún kan lé ní àádọ́rùn-ún.

Ní kété tí Olóyè Adegboyega Omiyale papòdà, ẹni tí ó gba ipò rẹ̀ tí ó tún jẹ́ ẹni tí kò bá jẹ́ ọba lèyín tí Olúbàdàn ìgbà náà, Ọba Samuel Odulana Odugade, ogójì Olúbàdàn ni Olóyè Omowale Ikúyẹ̀, ọ̀tún Olúbàdàn ṣùgbọ́n òun náà kò ní àǹfààní láti dé adé Olúbàdàn kí ọ lọ́jọ́ tó dé.

Ògúnjọ́, oṣù Kejìlá , lẹ́yìn ọjọ́ kẹtàlá tí olóyè Omiyale papòdà ni òun náà papòdà.

Sì ìyàlẹ́nu, ọjọ́ kọkàndínlógún oṣù Kínní ọdún 2016 nígbà tí ó pè oṣù méjì gérégé lẹ́yìn tí olóyè Kuyẹ papòdà, Ọba Samuel Odulana Odugade wàjà ní ẹni ọdún kan ó lé ní ọgọ́rùn-ún.

Ikú àwọn akọni mẹ́tẹ̀ẹ̀ta yìí jẹ́ ọ̀kan lára ìṣẹ̀lẹ̀ mánigbàgbé ní ilẹ̀ Ìbàdàn.

Èyí gan-an ni ó fún Ọba Saliu Adetunji Akanmu ní ànfàní láti di Olúbàdàn gẹ́gẹ́ bí Olúbàdàn ìkọkànlélógójì ní ọdún 2016.

Kí Ni 900 Ní Yorùbá?
08/10/2025

Kí Ni 900 Ní Yorùbá?

Address

Beere, Mapo
Ibadan

Alerts

Be the first to know and let us send you an email when ALAWIYE Blog posts news and promotions. Your email address will not be used for any other purpose, and you can unsubscribe at any time.

Share