Yoruba Broadcasting Network YBN

Yoruba Broadcasting Network YBN Be free

IROYIN TONI LORI YBN
17/07/2025

IROYIN TONI LORI YBN

LATEST & TRENDING NEWS FOR THE DAY...IROYIN AKOJOPO AGBEYEWO LORI YBN..NIGERIA & YORUBA NATION NEWS LINK: https://youtu.be/yIPTIC_m47QFOR M...

16/07/2025

ÀKÓJỌPỌ̀ ÌRÒYÌN ÒWÚRỌ̀ ÒNÍ ỌJỌ́ KẸRÌNDÍNLÓGÚN OṢÙ KÉJE ỌDÚN 2025

1. ÀÀRẸ BỌ́LÁ TINÚBÚ ÀTÀWỌN ADARÍ ORÍLẸ̀ ÈDÈ ÁFRÍKÀ GBOGBO TI DÁGBÉRE FÚN ÀÀRẸ TẸ́LẸ̀ LÓRÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ TÓ DI OLÓÒGBÉ, AJAGUNFẸ̀YÌNTÌ MÙHÁMMÁDÙ BÙHÁRÍ PÉ Ó DÌGBÓṢE LÁSÌKÒ ÈTÒ ÌSÌNKÚ TÍ WỌ́N ṢE FÚN LÁNÀÁ NÍ DAURA

2. OLÓYÈ ÀGBÀ KAN TÓ TÚN JẸ́ OLÙDÁSÍLẸ̀ ILÉ Ẹ̀KỌ́ GÍGA ALÁDÀNÍ AFẸ́ BABALỌLÁ TI SỌ̀RỌ̀ JÁDE PÉ ORÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ TI PÀDÁNÙ ÈNÌYÀN TÓ YÀTỌ̀, OLÙFARAJÌN, ỌMỌLÚWÀBÍ TÍ KÒ LÁFIWÉ TORÍ PÉ ÀÀRẸ TẸ́LẸ̀ TÓ DI OLÓÒGBÉ LÓRÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ, AJAGUNFẸ̀YÌNTÌ MÙHÁMMÁDÙ BÙHÁRÍ ṢIṢẸ́ TAKUNTAKUN LÁTI KOJÚ GBOGBO ÌWÀ ÌBÀJẸ́ TÓ Ń ṢẸLẸ̀ LÁWỌN Ẹ̀KA ÈTÒ ÌJỌBA LÓRÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ

3. ÀWỌN ALÁGBÀTÀ EPO KÉ GBÀJARÈ SÍTA FẸ̀HỌ́NÚHÀN LÁTARI BÍ OLÙDÁSÍLẸ̀ ILÉ IṢẸ́ DANGOTE, ALIKO DANGOTE ṢE SỌ PÉ ÒUN MÁA GBÉ OWÓ AFẸ́FẸ́ ÌDÁNÁ WÁLẸ̀

4. ÀGBARÍJỌPỌ̀ ẸGBẸ́ ÀWỌN ÒṢÌṢẸ́ ÌPÍNLẸ̀ ÒGÙN TI SỌ PÉ ÀWỌN Ò NÍ PADÀ SẸ́NÚ IṢẸ́ BÍ ÌJỌBA ÌPÍNLẸ̀ ÒGÙN LÁBẸ́ ÌṢÈJỌBA GÓMÌNÀ DÀPỌ̀ ABÍỌ́DÚN Ò BÁ TÈTÈ WÁ ǸKAN ṢE SÍ Ọ̀RỌ̀ OWÓ ÌFẸ̀YÌNTÌ TÍ ÀWỌN Ń JÀ LÉ LÓRÍ LÁTI ỌDÚN PÚPỌ̀ WÁ

5. ALÁKÒÓSO TẸ́LẸ̀ FÚN ÈTÒ ÌKÀNSÍRAẸNI LÓRÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ, Ọ̀JỌ̀GBỌ́N ISA ALI IBRAHIM PANTAMI TI GBÓRÍYÌN FÚN ÀÀRẸ ÀNÁ LÓRÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ TÓ DI OLÓÒGBÉ, AJAGUNFẸ̀YÌNTÌ MÙHÁMMÁDÙ BÙHÁRÍ PÉ ỌMỌLÚWÀBÍ ÀTI ÈNÌYÀN TÍ ÌGBÉ AYÉ RẸ̀ WU ÈNÌYÀN NI

6. OLÓKOÒWÒ TÓ LÓWÓ JÙ LỌ LÓRÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ, ALIKO DANGOTE TI RỌ GBOGBO ÀWỌN BỌ̀RỌ̀KÌNÍ ORÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ LÁTI MÁA DÁ IṢẸ́ SÍLẸ̀ KÍ WỌ́N SÌ MÁA ṢE ÒWÒ WỌN LÓRÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ KÍ WỌ́N YÉ LỌ́ SÍ ILẸ̀ ÒKÈÈRÈ

7. ÌJỌBA ÀPAPỌ̀ ORÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ LÁTI ẸNU ALÁGA ÌGBÌMỌ̀ TÓ Ń RÍ SÍ Ọ̀RỌ̀ IṢẸ́ NÍLÉ ÌGBÌMỌ̀ AṢÒFIN, AṢÒFIN BARINADA MPIGI TI SỌ PÉ ÀWỌN IṢẸ́ ÀKÀNṢE ÒPÓPÓNÀ ÌJỌBA ÀPAPỌ̀ TÓ TÓ IRÍNWÓ ÀTI OGÚN NI WỌ́N TI DI PÍPARÍ LÉYÌÍ TÍ ÀWỌN KÀN ṢÌ Ń LỌ LỌ́WỌ́ LÁÀRÍN ỌDÚN MÉJÌ ÌṢÈJỌBA ÀÀRẸ BỌ́LÁ TINÚBÚ

8. OLÚWÒ TI ÌLÚ ÌWÓ, ỌBA ABDULROSHEED ÀKÀNBÍ TI ṢÀPÈJÚWE ÈTÒ ÌSÌNKÚ TÍ WỌ́N ṢE FÚN ỌBA SÍKÍRÙ ADÉTỌ́NÀ, AWÙJALẸ̀ TI ILẸ̀ ÌJẸ̀BÚ NÍ ÌLÀNÀ Ẹ̀SÌN MÙSÙLÙMÍ GẸ́GẸ́ BÍ ÒMÌNIRA ÀWỌN ỌBA ILẸ̀ YORÙBÁ KÚRÒ LỌ́WỌ́ ẸBỌ RÍRÚ ÀTI ÌṢẸ̀ṢE

9. LÁTARI ÌDÁKÚREKÚ INÁ ỌBA TÓ Ń FI ÌGBÀ GBOGBO ṢẸLẸ̀ LÓRÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ, ÀWỌN ILÉ Ẹ̀KỌ́ GÍGA, ILÉ IṢẸ́ ÌKÀNSÍRA ẸNI MTN, ILÉ Ẹ̀KỌ́ ÀWỌN Ẹ̀ṢỌ́ ALÁÀBÒ ORÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ (NDA) ÀTÀWỌN ILÉ IṢẸ́ BÍI MẸ́RÌNDÍNLÓGÚN KAN TI BẸ̀RẸ̀ SÍ NÍ PÈSÈ INÁ MỌ̀NÀMỌ́NÁ FÚN ARA WỌN

10. IMAM ÀGBÀ MUHAMMAD MURTADHA OBHAKHOBO NÍ MỌ́ṢÁLÁṢÍ ÀPAPỌ̀ TÓ WÀ NÍ UROMI NÍ ÌPÍNLẸ̀ EDO TI KÉ GBÀJARÈ SÍTA PÉ ÒUN SAN OWÓ TÓ TÓ MÍLÍỌ́NÙ MẸ́FÀ ÀTI ÀBỌ̀ ( #6.5million) GẸ́GẸ́ BÍ OWÓ ÌDÁSÍLẸ̀ LỌ́WỌ́ ÀWỌN AJÍNIGBÉ KÌÍ ṢE ÀWỌN ỌLỌ́PÀÁ LÓ GBA ÒUN KALẸ̀ GẸ́GẸ́ BÍ WỌ́N ṢE Ń KÉDE Ẹ̀ KIRI

ÌKÀNNÌ AMÓHÙN-MÁWÒRÁN YORÙBÁ BROADCASTING NETWORK (YBN) LATI Ń KỌ ÀWỌN ÀKÓJỌPỌ̀ ÌRÒYÌN OLÓJOJÚMỌ́ YÌÍ JÁDE FÚN ÌGBÁDÙN Ẹ̀YIN OLÓLÙFẸ́ WA, Ẹ ṢÉ PÚPỌ̀ FÚN ÌFẸ́ TÍ Ẹ NÍ SÍ WA, ÀJỌṢE WA Ò NÍ BÀJẸ́

IROYIN TONI LORI YBN
16/07/2025

IROYIN TONI LORI YBN

LATEST & TRENDING NEWS FOR THE DAY...IROYIN AKOJOPO AGBEYEWO LORI YBN..NIGERIA & YORUBA NATION NEWS LINK: https://youtu.be/zQOiKeqjpQgFOR M...

15/07/2025

ÀKÓJỌPỌ̀ ÌRÒYÌN ÒWÚRỌ̀ ÒNÍ ỌJỌ́ KẸẸ̀DÓGÚN OṢÙ KÉJE ỌDÚN 2025

1. ÌJỌBA ÀPAPỌ̀ ORÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ TI KÉDE ÒNÍ ỌJỌ́ KẸẸ̀DÓGÚN OṢÙ KÉJE GẸ́GẸ́ BÍ ỌJỌ́ ÌSINMI LẸ́NU IṢẸ́ FÚN GBOGBO ỌMỌ ORÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ LÁTI BỌ̀WỌ̀ FÚN AJAGUNFẸ̀YÌNTÌ MÙHÁMMÁDÙ BÙHÁRÍ TÓ DI OLÓÒGBÉ ÀTI LÁTI ṢE ÈTÒ ÌSÌNKÚ FÚN-UN

2. OLÓRÍ ORÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ TẸ́LẸ̀, Ọ̀GAGUNFẸ̀YÌNTÌ ABDULSALAMI ÀBÚBÁKÀR TI SỌ̀RỌ̀ SÍTA PÉ ILÉ ÌWÒSÀN KANNÁ LÒUN WÀ PẸ̀LÚ MÙHÁMMÁDÙ BÙHÁRÍ KÍ WỌ́N TÓ NÍ KÍ ÒUN MÁA LỌ ILÉ PÉ ARA ÒUN TI YÁ

3. ALÁKÉ TI ILẸ̀ Ẹ̀GBÁ, ỌBA ADÉDỌ̀TUN ÀRẸ̀MÚ GBÁDÉBỌ̀ TI JẸ́ KÓ DI MÍMỌ̀ PÉ ÒUN KÒ KÁBÀMỌ́ LÁTI BÁ AJAGUNFẸ̀YÌNTÌ MÙHÁMMÁDÙ BÙHÁRÍ TÓ DI OLÓÒGBÉ ṢIṢẸ́ PAPỌ̀ LÁSÌKÒ TÓ WÀ LÓRÍ ÀLÉÉFÀ GẸ́GẸ́ BÍ OLÓRÍ ORÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ LÁSÌKÒ ÌṢÈJỌBA OLÓGUN, Ó NÍ Ọ̀GÁ TÓ DA PÚPỌ̀ NI

4. ÀWỌN ỌMỌ OLÓGUN ORÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ DÁ ÀWỌN ONÍṢẸ̀ṢE LỌ́WỌ́ KỌ́ LÁTI MÁ KÓPA NÍNÚ ÌSÌNKÚ ỌBA SÍKÍRÙ ADÉTỌ̀NÀ TÍÍ ṢE AWÙJALẸ̀ ILẸ̀ ÌJẸ̀BÚ TÓ WÀJÀ

5. ÀJỌ TÓ Ń RÍ SÍ ÈTÒ ÌDÌBÒ LÓRÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ (INEC) TI JẸ́ KÓ DI MÍMỌ̀ PÉ ÈTÒ ÌFORÚKỌSÍLẸ̀ FÚN KÁÀDÌ ÌDÌBÒ ALÁLÒPẸ́ (PVC) MÁA TÓ BẸ̀RẸ̀ LÓṢÙ KẸ́JỌ ỌDÚN YÌÍ

6. AGBẸJỌ́RÒ AJÀFẸ́TỌ̀ ỌMỌNÌYÀN TÍ Ó TÚN FI ÌGBÀ KAN JẸ́ ALÁGA ÀJỌ TÓ Ń RÍ SÍ Ọ̀RỌ̀ ỌMỌNÌYÀN LÓRÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ, Ọ̀JỌ̀GBỌ́N CHIDI ODINKALU TI SỌ ÒGÚLÙSI Ọ̀RỌ̀ SÍ ÀWỌN OLÓṢÈLÚ ORÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ PÉ KÍ WỌ́N ṢE ÀTÚNṢE ÀWỌN ILÉ ÌWÒSÀN TÓ WÀ LÓRÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ TÀBÍ KÍ WỌ́N MÁA DÌ WỌ́N MỌ́ ẸRÙ FI WỌ́N RÁNṢẸ́ LẸ́YÌN TÍ WỌ́N BÁ TI GBẸ́MÌ MÌ NÍ ILẸ̀ ÒKÈÈRÈ

7. ÌJỌBA ÌPÍNLẸ̀ KÁNÒ TI ṢÀTÌLẸYÌN FÚN ÌDÁSÍLẸ̀ ỌLỌ́PÀÁ ÌPÍNLẸ̀, BẸ́Ẹ̀ NÁÀ LÓ WÁ Ń BÉÈRÈ FÚN ÀFIKÚN ÌJỌBA ÌPÍNLẸ̀ ÀTI ÌDÁSÍLẸ̀ ÀWỌN ÌJỌBA ÌBÍLẸ̀ MẸ́RÌNDÍNLỌ́GBỌ̀N

8. ÀGBARÍJỌPỌ̀ ẸGBẸ́ ÀWỌN ÒṢÌṢẸ́ ÌJỌBA ÌPÍNLẸ̀ ÒGÙN TI KÉDE ÌYANṢẸ́LÓDÌ ALÁÌNÍGBÈǸDEKE BẸ̀RẸ̀ LÁTI ÒNÍ ỌJỌ́ ÌṢẸGUN TÍÍ ṢE ỌJỌ́ KẸẸ̀DÓGÚN OṢÙ KÉJE

9. ÀJỌ TÓ Ń RÍ SÍ OUN TÓ NÍ ṢE PẸ̀LÚ INÁ ỌBA LÓRÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ (NERC) TI JẸ́ KÓ DI MÍMỌ̀ PÉ ÌJỌBA ÀPAPỌ̀ NÁ TÍRÍLÍỌ́NÙ KAN ÀTI MẸ́RÌNLÉLÁÀDỌ́RUN NÁÍRÀ GẸ́GẸ́ BÍ OWÓ ÌRÀNWỌ́ ORÍ INÁ MỌ̀NÀMỌ́NÁ LỌ́DÚN 2024

10. ILÉ IṢẸ́ ỌLỌ́PÀÁ ÌPÍNLẸ̀ ÒGÙN TI KÉDE PÉ WỌ́N Ń WÁ ÀWỌN ỌMỌ ẸLẸ́GBẸ́ ÒKÙNKÙN MẸ́RIN KAN TÍ WỌ́N ṢEKÚ PA ỌKÙNRIN KÀN ẸNI ỌDÚN MẸ́RÌNLÉLÓGÓJÌ TÍ ORÚKỌ RẸ̀ Ń JẸ́ BÀṢÍRÙ SÈÍDÙ TÍÍ ṢE ỌMỌ ẸGBẸ́ ÒKÙNKÙN ẸIYẸ NÍ ÌLÚ ATAN-Ọ̀TÀ

ÌKÀNNÌ AMÓHÙN-MÁWÒRÁN YORÙBÁ BROADCASTING NETWORK (YBN) LATI Ń KỌ ÀWỌN ÀKÓJỌPỌ̀ ÌRÒYÌN OLÓJOJÚMỌ́ YÌÍ JÁDE FÚN ÌGBÁDÙN Ẹ̀YIN OLÓLÙFẸ́ WA, Ẹ ṢÉ PÚPỌ̀ FÚN ÌFẸ́ TÍ Ẹ NÍ SÍ WA, ÀJỌṢE WA Ò NÍ BÀJẸ́

IROYIN TONI LORI YBN
15/07/2025

IROYIN TONI LORI YBN

LATEST & TRENDING NEWS FOR THE DAY...IROYIN AKOJOPO AGBEYEWO LORI YBN..NIGERIA & YORUBA NATION NEWS LINK: https://youtu.be/zWG1PTxsaBMFOR M...

14/07/2025

ÀKÓJỌPỌ̀ ÌRÒYÌN ÒWÚRỌ̀ ÒNÍ ỌJỌ́ KẸRÌNLÁ OṢÙ KÉJE ỌDÚN 2025

1. ÀÀRẸ ORÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ, AṢÍWÁJÚ BỌ́LÁ AHMED TINÚBÚ ÀTÀWỌN ÀÀRẸ TÍ WỌ́N TI ṢE ÌJỌBA LÓRÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ KỌJÁ BÍI OLÓYÈ OLÚṢẸ́GUN ỌBÁSANJỌ́, GOODLUCK EBELE JONATHAN, IBRAHIM BÀBÁNŃGÍDÁ ÀTÀWỌN MÌÍRÀN TI KẸ́DÙN IKÚ ÀÀRẸ TẸ́LẸ̀ LÓRÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ, AJAGUNFẸ̀YÌNTÌ MÙHÁMMÁDÙ BÙHÁRÍ TÓ DI OLÓÒGBÉ NÍ ILÉ ÌWÒSÀN KAN TÓ WÀ NÍ LONDON LÁNÀÁ

2. GÓMÌNÀ ÌPÍNLẸ̀ ÒGÙN, ỌMỌBA DÀPỌ̀ ABÍỌ́DÚN TI KẸ́DÙN Ó SÌ TI KÉDE ÌPAPÒDÀ ỌBA ALAYÉ TI ILẸ̀ ÌJẸ̀BÚ, ỌBA SÍKÍRÙ KÁYỌ̀DÉ ADÉTỌ̀NÀ TÓ WÀJÀ LÁNÀÁ

3. ÀÀRẸ ORÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ, AṢÍWÁJÚ BỌ́LÁ AHMED TINÚBÚ TI BALẸ̀ GÙDẸ̀ PADÀ SÍ ORÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ LẸ́YÌN ÀBẸ̀WÒ ÀTI ÀWỌN ÌPÀDÉ TÓ LỌ ṢE NÍ SAINT LUCIA LÓRÍLẸ̀ ÈDÈ BRAZIL

4. ÀÀRẸ BỌ́LÁ TINÚBÚ TI KÍ Ọ̀JỌ̀GBỌ́N WỌLÉ ṢÓYÍNKÁ KÚ ORÍIRE ỌDÚN MỌ́KÀNLÉLÁÀDỌ́RÙN-ÚN TÓ Ń PÉ LÓKÈ EÈPẸ̀

5. OLÚBÀDÀN TUNTUN, ỌBA RÀṢÍDÌ LÁDỌJÀ TI SÚN ỌJỌ́ TÓ MÁA PADÀ SÍ ÌBÀDÀN NÍ ÌPÍNLẸ̀ Ọ̀YỌ́ SÍWÁJÚ DI Ẹ̀YÌN ỌJỌ́ MỌ́KÀNLÉLÓGÚN TÍ WỌ́N BÁ KẸ́DÙN IKÚ OLÚBÀDÀN ÌYẸN ỌBA OWÓLABÍ ỌLÁKÙLẸ́YÌN TÓ WÀJÀ

6. ÌJỌBA ÌPÍNLẸ̀ ABIA, ADAMAWA ÀTÀWỌN ÀWỌN ÌJỌBA ÌPÍNLẸ̀ MÉJE MÌÍRÀN Ò TÍÌ BẸ̀RẸ̀ SI NÍ SAN ẸGBẸ̀RÚN LỌ́NÀ ÀÁDỌ́RUN NÁÍRÀ OWÓ OṢÙ ÀWỌN ÒṢÌṢẸ́ TÓ KÉRÉ JÙ LỌ FÚN ÀWỌN OLÙKỌ́ ÌPÍNLẸ̀ WỌN

7. ALÁGA FÌDÍẸ́ ẸGBẸ́ ÒṢÈLÚ AFRICAN DEMOCRATIC CONGRESS (ADC) AṢÒFIN DAVID MARK TI JẸ́ KÓ DI MÍMỌ̀ PÉ ÌṢÈJỌBA TÓ WÀ LÓRÍ IPÒ BÁYÌÍ TI Ń GBÌYÀNJÚ ÀTI LO ILÉ ẸJỌ́ LÁTI DABARÚ BÍ ẸGBẸ́ ÒṢÈLÚ AFRICAN DEMOCRATIC CONGRESS (ADC) ṢE Ń GBÈRÚ SI

8. ALÁGA IGUN KÀN NÍNÚ ẸGBẸ́ ÒṢÈLÚ LABOUR PARTY, JULIUS ABURE TI ṢE ÌPÀDÉ PAPỌ̀ PẸ̀LÚ ALÁKÒÓSO LÓLÚ ÌLÚ WA ÀBÚJÁ, NYESOM WIKE LÓRÍ Ọ̀RỌ̀ TÍ WỌN KÒ TÍÌ FI LÉDE

9. ÀJỌ TÓ Ń RÍ SÍ Ẹ̀TỌ́ ÀWỌN ẸLẸ́SÌN MÙSÙLÙMÍ Ẹ̀KA TI ÌPÍNLẸ̀ ÒGÙN (MURIC) TI KÉ GBÀJARÈ SÍTA LÓRÍ BÓ ṢE JẸ́ PÉ ÀWỌN ẸLẸ́SÌN KRISTẸNI TÍ WỌ́N FI SÓRÍ IPÒ TÓ GA JÙLỌ LÁWỌN ILÉ IṢẸ́ ÌJỌBA ÌPÍNLẸ̀ ÒGÙN PỌ̀ JU ÀWỌN ẸLẸ́SÌN MÙSÙLÙMÍ LỌ

10. ẸGBẸ́ ÒṢÈLÚ ALL PROGRESSIVES CONGRESS (APC) NÍ ÌPÍNLẸ̀ Ọ̀ṢUN TI SỌ PÉ ÌRÒYÌN TÓ JÌNNÀ SÍ ÒTÍTỌ́ NI GÓMÌNÀ ÌPÍNLẸ̀ Ọ̀ṢUN, ADÉMỌ́LÁ ADÉLÉKÈ Ń GBÉ KIRI PÉ ÒUN TI DIGBÁDAGBỌ̀N ÒUN KÚRÒ NÍNÚ ẸGBẸ́ ÒṢÈLÚ PEOPLES DEMOCRATIC PARTY (PDP) LỌ SÍNÚ ẸGBẸ́ ÒṢÈLÚ ALL PROGRESSIVES CONGRESS (APC)

ÌKÀNNÌ AMÓHÙN-MÁWÒRÁN YORÙBÁ BROADCASTING NETWORK (YBN) LATI Ń KỌ ÀWỌN ÀKÓJỌPỌ̀ ÌRÒYÌN OLÓJOJÚMỌ́ YÌÍ JÁDE FÚN ÌGBÁDÙN Ẹ̀YIN OLÓLÙFẸ́ WA, Ẹ ṢÉ PÚPỌ̀ FÚN ÌFẸ́ TÍ Ẹ NÍ SÍ WA, ÀJỌṢE WA Ò NÍ BÀJẸ́

IROYIN TONI LORI YBN
14/07/2025

IROYIN TONI LORI YBN

LATEST & TRENDING NEWS FOR THE DAY...IROYIN AKOJOPO AGBEYEWO LORI YBN..NIGERIA & YORUBA NATION NEWS LINK: https://youtu.be/Sdg4mHTMonoFOR M...

13/07/2025

ÀKÓJỌPỌ̀ ÌRÒYÌN ÒWÚRỌ̀ ÒNÍ ỌJỌ́ KẸTÀLÁ OṢÙ KÉJE ỌDÚN 2025

1. ÀÀRẸ ORÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ, AṢÍWÁJÚ BỌ́LÁ AHMED TINÚBÚ TI GBÉRA KÚRÒ LÓRÍLẸ̀ ÈDÈ BRAZIL TÍ YÓÒ SÍ BALẸ̀ SÍLÙ ÀBÚJÁ TÍÍ ṢE OLÚ ORÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ LẸ́YÌN ÀWỌN ÌPÀDÉ ÀBẸ̀WÒ TÓ LỌ ṢE

2. ÀWỌN OLÙGBÉ ÌPÍNLẸ̀ KÁNÒ ṢE ÀKÀNṢE ÀDÚRÀ KÍ ÒJÒ LÈ RỌ̀ NÍ ÌPÍNLẸ̀ NÁÀ

3. ẸGBẸ́ ÒṢÈLÚ ALL PROGRESSIVES CONGRESS (APC) LÉWÁJÚ GBOGBO ÌDÌBÒ TÍ WỌ́N DÌ JÁKÈJÁDÒ GBOGBO ÀWỌN ÌJỌBA ÌBÍLẸ̀ MẸ́TÀDÍNLỌ́GỌ́TA NÌ ÌPÍNLẸ̀ ÈKÓ PẸ̀LÚ BÍ ÀWỌN OLÙDÌBÒ Ò ṢE JÁDE PÚPỌ̀

4. LÓRÍ ÈTÒ ÌDÌBÒ ÀPAPỌ̀ TÓ MÁA WÁYÉ LỌ́DÚN 2027, ÀWỌN ỌMỌ ẸGBẸ́ ÒṢÈLÚ PEOPLES DEMOCRATIC PARTY (PDP) LẸ́KÙN GÚÚSÙ ÌWỌ̀ OÒRÙN ORÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ TAKO ẸGBẸ́ ÒṢÈLÚ ALÁJÙMỌ̀ṢEPỌ̀ TÍ ÀLHÁJÌ ÀTÍKÙ ÀBÚBÁKÀR, PETER OBI ÀTI ELRUFAI DÁ SÍLẸ̀

5. ẸGBẸ́ ÒṢÈLÚ PEOPLES DEMOCRATIC PARTY (PDP) NÍ ÌPÍNLẸ̀ YOBE TI SỌ PÉ ÀWỌN Ò DARAPỌ̀ MỌ́ ÀKÓJỌPỌ̀ ẸGBẸ́ ÒṢÈLÚ ALÁJÙMỌ̀ṢEPỌ̀

6. GÓMÌNÀ ÌPÍNLẸ̀ Ọ̀ṢUN, ADÉMỌ́LÁ ADÉLÉKÈ TI JẸ́ KÓ DI MÍMỌ̀ PÉ ÒUN ṢÌ Ń ṢIṢẸ́ ÌWÁDÌÍ LỌ́WỌ́ LÓRÍ ÈRÓŃGBÀ BÓYÁ ÒUN FẸ́ FI ẸGBẸ́ ÒṢÈLÚ PEOPLES DEMOCRATIC PARTY (PDP) SÍLẸ̀ BÍ Ó TILẸ̀ JẸ́ PÉ ÀWỌN ỌMỌ ẸGBẸ́ ÒṢÈLÚ ÒUN NÍ ÌPÍNLẸ̀ Ọ̀ṢUN TI ṢÈLÉRÍ LÁTI TẸ̀LÉ ÒUN LỌ SÍ ẸGBẸ́ ÒṢÈLÚ TÍ ÒUN BÁ LỌ

7. GÓMÌNÀ TẸ́LẸ̀ NÍ ÌPÍNLẸ̀ ÈKÓ, RÁJÍ FÁṢỌLÁ KỌ̀ LÁTI YỌJÚ SÍBI ÈTÒ ÌDÌBÒ ÌJỌBA ÌBÍLẸ̀ TÍ WỌ́N DÌ NÍ ÌJỌBA ÌBÍLẸ̀ TÓ WÀ NÍ ÌPÍNLẸ̀ ÈKÓ

8. AṢÒFIN ÀGBÀ KINGIBE TI FI ẸGBẸ́ ÒṢÈLÚ LABOUR PARTY SÍLẸ̀ LỌ SÍNÚ ẸGBẸ́ ÒṢÈLÚ AFRICAN DEMOCRATIC CONGRESS (ADC)

9. FẸ́MI GBÀJÀBÍÀMÍLÀ TI SỌ PÉ ẸGBẸ́ ÒṢÈLÚ AFRICAN DEMOCRATIC CONGRESS (ADC) Ò NÍ IBÌ KANKAN TÍ WỌ́N Ń LỌ BẸ́Ẹ̀ SÌ NI WỌN Ò NÍ RÍ ỌWỌ́ MÚ NÍNÚ ÌDÌBÒ ÀPAPỌ̀ TÓ MÁA WÁYÉ LỌ́DÚN 2027

10. ILÉ ẸJỌ́ TI DÁJỌ́ IKÚ FÚN ÀWỌN ỌMỌ ỌMỌKÙNRIN MÉJÌ NÍNÚ ÀWỌN MẸ́TA TÍ WỌ́N LỌ́WỌ́ NÍNÚ IKÚ SỌ̀FÍÁ NÍ ÌLÚ ABẸ́ÒKÚTA LÉYÌÍ TÍ WỌ́N NÍ KÍ Ọ̀KAN TÓ KÙ LỌ MÁA LO GBOGBO ÌGBÉSÍ AYÉ Ẹ̀ TÓ KÙ NÍNÚ ỌGBÀ Ẹ̀WỌ̀N

ÌKÀNNÌ AMÓHÙN-MÁWÒRÁN YORÙBÁ BROADCASTING NETWORK (YBN) LATI Ń KỌ ÀWỌN ÀKÓJỌPỌ̀ ÌRÒYÌN OLÓJOJÚMỌ́ YÌÍ JÁDE FÚN ÌGBÁDÙN Ẹ̀YIN OLÓLÙFẸ́ WA, Ẹ ṢÉ PÚPỌ̀ FÚN ÌFẸ́ TÍ Ẹ NÍ SÍ WA, ÀJỌṢE WA Ò NÍ BÀJẸ́

IROYIN TONI LORI YBN
13/07/2025

IROYIN TONI LORI YBN

LATEST & TRENDING NEWS FOR THE DAY...IROYIN AKOJOPO AGBEYEWO LORI YBN..NIGERIA & YORUBA NATION NEWS LINK: https://youtu.be/J4hDTjt5DlUFOR M...

12/07/2025

ÀKÓJỌPỌ̀ ÌRÒYÌN ÒWÚRỌ̀ ÒNÍ ỌJỌ́ KEJÌLÁ OṢÙ KÉJE ỌDÚN 2025

1. ÀÀRẸ ORÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ, AṢÍWÁJÚ BỌ́LÁ AHMED TINÚBÚ TI BỌWỌ́ LU AYẸYẸ ÌFÀMÌ Ẹ̀YẸ DÁ ÀWỌN OGBÓNTÀRIGÌ OLÓRIN ILẸ̀ ÁFRÍKÀ LỌ́LÁ ÌYẸN AFRIMA 2025 TÓ MÁA WÁYÉ NÍ ÌPÍNLẸ̀ ÈKÓ

2. OLÓRÍ ÀWỌN ADÁJỌ́ NÍ ÌPÍNLẸ̀ ÈKÓ, KAZEEM ALOGBA TI GBÉ ILÉ ẸJỌ́ TÓ Ń GBỌ́ AWUYEWUYE LẸ́YÌN ÌDÌBÒ KALẸ̀ NÍ ERÉKÙṢÙ ÌPÍNLẸ̀ ÈKÓ ÀTI ÌKẸJÀ LÁTI GBỌ ẸJỌ́ TÓ BÁ SÚYỌ LẸ́YÌN ÌDÌBÒ TÓ MÁA WÁYÉ LÁWỌN ÌJỌBA ÌBÍLẸ̀ TÓ WÀ NÍ ÌPÍNLẸ̀ ÈKÓ

3. ÀWỌN ALÁTÌLẸYÌN ÀTÀWỌN ÈNÌYÀN KAN LÓRÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ TI BẸ̀RẸ̀ SI NÍ GBÓRÍYÌN FÚN ADÍJEDUPÒ ÀÀRẸ LỌ́DÚN 2023 LÁBẸ́ ẸGBẸ́ ÒṢÈLÚ LABOUR PARTY ÌYẸN PETER OBI LÁTARI BÍ Ó ṢE Ń GBÉ OÚNJẸ FÚN ÀWỌN ÈNÌYÀN NÍBI AYẸYẸ KAN TÓ WÁYÉ NÍ UMUCHIMA NÍ ÌPÍNLẸ̀ IMO

4. ÀJỌ TÓ Ń WO ṢÀÀKUN BÍ OJÚ ỌJỌ́ ṢE RÍ (NIMET) TI TARI ÀTẸ̀JÁDE KAN SÍTA PÉ OMÍYALÉ Ọ̀GBÀRÁ YA ṢỌ́Ọ̀BÙ MÁA ṢỌṢẸ́ LÁWỌN ÌPÍNLẸ̀ KAN TÓ MÁA TÓ OGÚN LÓRÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ FÚN ÌDÍ ÈYÍ, KÍ ÀWỌN TÓ BÁ WÀ NÍ AGBÈGBÈ TÍ Ẹ̀KÚN OMI TI MÁA Ń ṢẸLẸ̀ Ó TÈTÈ KÚRÒ LÁWỌN AGBÈGBÈ NÁÀ NÍ KÍÁKÍÁ

5. GÓMÌNÀ ÌPÍNLẸ̀ EDO, MONDAY OKPEBHOLO TI SỌ̀RỌ̀ JÁDE PÉ ÒUN TI ṢE TÁN LÁTI TANNÁ WÁDÌÍ GÓMÌNÀ TẸ́LẸ̀ NÍ ÌPÍNLẸ̀ NÁÀ ÌYẸN GODWIN OBASEKI LẸ́YÌN TÍ ILÉ ẸJỌ́ TÓ GA JÙLỌ NÍLẸ̀ WA TI FI ÈTÒ ÌDÌBÒ TÓ GBÉ E WỌLÉ GẸ́GẸ́ BÍ GÓMÌNÀ ÌPÍNLẸ̀ EDO MÚLẸ̀

6. ILÉ IṢẸ́ ÀÀRẸ ORÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ TI SỌ̀RỌ̀ PÉ IGBÁKEJÌ ÀÀRẸ ORÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ, KASHIM SHETTIMA Ò BẸNU ÀTẸ́ LU ÀÀRẸ BỌ́LÁ TINÚBÚ LÓRÍ LỌGBỌLỌGBỌ TÓ Ń ṢẸLẸ̀ NÍ ÌPÍNLẸ̀ RIVERS

7. ẸGBẸ́ ÒṢÈLÚ AFRICAN DEMOCRATIC CONGRESS (ADC) TI DÁ ÈSÌ Ọ̀RỌ̀ PADÀ FÚN ILÉ IṢẸ́ ÀÀRẸ ORÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ PÉ ÒÓTỌ́ Ọ̀RỌ̀ NI IGBÁKEJÌ ÀÀRẸ KASHIM SHETTIMA SỌ PÉ ÀÀRẸ TINÚBÚ Ò NÍ ÀṢẸ LÁTI YỌ SIMINALAYI FUBARA KÚRÒ LÓRÍ IPÒ GẸ́GẸ́ BÍ GÓMÌNÀ ÌPÍNLẸ̀ RIVERS

8. ILÉ IṢẸ́ ELÉPO ILẸ̀ WA (NNPCL) TI Ń GBÌYÀNJÚ ÀTI TA ÀWỌN ẸBU ÌFỌPO KAN LÓRÍLẸ̀ ÈDÈ YÌÍ LÁTARI ÀÌṢE DÉDÉ WỌN LẸ́YÌN TÍ WỌ́N NÁ OWÓ TÓ LÉ NÍ BÍLÍỌ̀NÙ MÉJÌDÍNLÓGÚN OWÓ ILẸ̀ ÒKÈÈRÈ ($18bn) LÁÌSÍ ÌYÀTỌ̀

9. GARBA SHEHU TÓ JẸ́ AGBẸNUSỌ FÚN ÀÀRẸ TẸ́LẸ̀ LÓRÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ TI SỌ PÉ ÌRÒYÌN ẸLẸ́JẸ̀ NI ÌRÒYÌN KAN TÓ Ń JÀ RÀN-ÌN RÀN-ÌN LÁSÌKÒ ÌṢÈJỌBA ÀÀRẸ MÙHÁMMÁDÙ BÙHÁRÍ PÉ ÈKÚTÉ ILÉ WỌ INÚ Ọ́FÌSÌ ÀÀRẸ TÓ WÀ NÍ A*O ROCK, Ó NÍ WỌ́N LO ÌRÒYÌN YÌÍ LÁTI LÈ MÚ KÍ ỌKÀN ÀWỌN ỌMỌ ORÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ Ó KÚRÒ NÍNÚ ÀÌLERA ÀÀRẸ MÙHÁMMÁDÙ BÙHÁRÍ LÁSÌKÒ NÁÀ NI

10. WÀHÁLÀ ŃLÁ BẸ́ SÍLẸ̀ NÍ ILÉ Ẹ̀KỌ́ GIRAMA KÀN TÓ WÀ NÍ ÌJỌBA ÌBÍLẸ̀ OJU NÍ ÌPÍNLẸ̀ BENUE NÍGBÀ TÍ AKẸ́KỌ̀Ọ́ KAN ỌMỌ ỌDÚN MẸ́RÌNDÍNLÓGÚN TÍ ORÚKỌ RẸ̀ Ń JẸ́ FRIDAY OGAMUDE LU OLÙKỌ́ RẸ̀ ARÁKÙNRIN OYIBE OYIBE ẸNI OMỌ́ MÁRÙNDÍNLÓGÓJÌ PA NÍTORÍ FÌLÀ TÍ OLÙKỌ́ NÁÀ GBÀ LỌ́WỌ́ RẸ̀

ÌKÀNNÌ AMÓHÙN-MÁWÒRÁN YORÙBÁ BROADCASTING NETWORK (YBN) LATI Ń KỌ ÀWỌN ÀKÓJỌPỌ̀ ÌRÒYÌN OLÓJOJÚMỌ́ YÌÍ JÁDE FÚN ÌGBÁDÙN Ẹ̀YIN OLÓLÙFẸ́ WA, Ẹ ṢÉ PÚPỌ̀ FÚN ÌFẸ́ TÍ Ẹ NÍ SÍ WA, ÀJỌṢE WA Ò NÍ BÀJẸ́

IROYIN TONI LORI YBN
12/07/2025

IROYIN TONI LORI YBN

LATEST & TRENDING NEWS FOR THE DAY...IROYIN AKOJOPO AGBEYEWO LORI YBN..NIGERIA & YORUBA NATION NEWS LINK: https://youtu.be/ppWiu5U363EFOR M...

11/07/2025

ÀKÓJỌPỌ̀ ÌRÒYÌN ÒWÚRỌ̀ ÒNÍ ỌJỌ́ KỌKÀNLÁ OṢÙ KÉJE ỌDÚN 2025

1. ÀÀRẸ ORÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ, AṢÍWÁJÚ BỌ́LÁ AHMED TINÚBÚ TI SỌ PÉ ÒUN Ò FÒFINDE FÍFI ÌWÉ ÀṢẸ ÌRÌNNÀ ỌLỌ́DÚN MÁRÙN-ÚN SÍTA FÁWỌN ÀWỌN ỌMỌ ORÍLẸ̀ ÈDÈ AMẸ́RÍKÀ LÁTARI ÀTÚNṢE TÍ WỌ́N ṢE LÁÌPẸ́ YÌÍ LÓRÍ ÌLÀNÀ ÌWÉ ÀṢẸ ÌRÌNNÀ LÁTI ILẸ̀ AMẸ́RÍKÀ

2. ÀJỌ ECOWAS TI JẸ́ KÓ DI MÍMỌ̀ PÉ OJÚ Ọ̀NÀ ONÍKÌLÓMÍTÀ ẸGBẸ̀RÚN KAN Ó LÉ TÓ JẸ́ OLÓPÒ MẸ́FÀ TÍ WỌ́N FẸ́ ṢE LÁTI ABIDJAN DÉ ÌPÍNLẸ̀ ÈKÓ TI WÀ NÍ IPELE ÀṢÉKÁGBÁ

3. ÀWỌN ỌMỌ ILÉ ÌGBÌMỌ̀ AṢÒFIN ÀGBÀ ILẸ̀ WA TI YAN AṢÒFIN ÀGBÀ LINCOLN BASSEY LÁTI RỌ́PÒ AṢÒFIN NATASHA AKPOTI-UDUAGHAN GẸ́GẸ́ BÍ ALÁGA FÚN ÌGBÌMỌ̀ TÓ Ń RÍ SÍ Ọ̀RỌ̀ ÀWỌN ORÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ TÓ WÀ NÍLẸ̀ ÒKÈÈRÈ ÀTI ÀWỌN ẸGBẸ́ TÍ KÌÍ ṢE TI ÌJỌBA

4. ILÉ ÌGBÌMỌ̀ AṢÒFIN ÀGBÀ ILẸ̀ WA TI KÉ SÍ ÌJỌBA ÀPAPỌ̀ LÁTI ṢE ÀTÚNṢE ÀTI ÌLÀNÀ ÌGBÉKALẸ̀ LẸ́KA ÌPÈSE INÁ MỌ̀NÀMỌ́NÁ LÓRÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ NÍPASẸ̀ ÀWỌN ILÉ IṢẸ́ TÍ WỌ́N Ń PÍNNÁ MỌ̀NÀMỌ́NÁ KÁÀKIRI

5. ILÉ ẸJỌ́ TÓ GA JÙLỌ NÍLẸ̀ WA TI FI ÈTÒ ÌDÌBÒ TÓ GBÉ MONDAY OKPEBHOLO TI INÚ ẸGBẸ́ ÒṢÈLÚ ALL PROGRESSIVES CONGRESS (APC) WỌLÉ GẸ́GẸ́ BÍ GÓMÌNÀ ÌPÍNLẸ̀ EDO MÚLẸ̀

6. ÀJỌ TÓ Ń RÍ SÍ ÈTÒ ÌDÁNWÒ TÓ NÍ ṢE PẸ̀LÚ ÀWỌN ONÍṢẸ́ ỌWỌ́ (NABTEB) TI FI ÈSÌ ÌDÁNWÒ SÍTA FÚN ÀWỌN TÓ BÁ FẸ WỌLÉ GẸ́GẸ́ BÍ AKẸ́KỌ̀Ọ́ SÁWỌN ILÉ Ẹ̀KỌ́ TÍ WỌ́N TI Ń KỌ́ṢẸ́ ỌWỌ́ LÓRÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ

7. ẸGBẸ́ ÀWỌN ONÍṢÈGÙN ÒYÌNBÓ LÓRÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ (NMA) TI SỌ́ DI MÍMỌ̀ PÉ ÀWỌN MÁA GÙNLÉ ÌYANṢẸ́LÓDÌ ALÁÌNÍ GBÈǸDEKE BÍ ÌJỌBA ÀPAPỌ̀ ORÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ BÁ KỌ̀ LÁTI YANJÚ ÀWỌN ÌṢÒRO KAN LẸ́KA NÁÀ TORÍ PÉ ÀWỌN TI ṢE SÙÚRÙ TÓ LÓRÍ ÀWỌN ÌLÀNÀ SÍSAN OWÓ OṢÙ WỌN

8. ÀGBARÍJỌPỌ̀ ẸGBẸ́ ÀWỌN GÓMÌNÀ LÁPÁ GÚÚSÙ ORÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ TI KÍ GÓMÌNÀ ÌPÍNLẸ̀ EDO MONDAY OKPEBHOLO KÚ ORÍIRE LÁTARI ÌJÁWÉ OLÚBORÍ RẸ̀ NÍLÉ ẸJỌ́ GÍGA JÙ LỌ NÍLẸ̀ WA

9. ÀJỌ AYÁNILÓWÓ LÁGBÀYÉ (IMF) TI FỌWỌ́ ÀTÌLẸYÌN WỌN SỌ̀YÀ FÚN ÀJỌ TÓ Ń RÍ SÍ ÌLÀNÀ ÌPAWÓWỌLÉ LÓRÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ (FIRS) LÁTARI ÌLÀNÀ ÌMÚGBÒÒRÒ TÍ WỌ́N FI Ń PAWÓ WỌLÉ LÓRÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ

10. GÓMÌNÀ ÌPÍNLẸ̀ ÒGÙN, ỌMỌBA DÀPỌ̀ ABÍỌ́DÚN TI RỌ ÀWỌN OLÓKOÒWÒ LÁTI ORÍLẸ̀ ÈDÈ BRAZIL LÁTI JỌ ṢIṢẸ́ PAPỌ̀ ṢE ÀGBÉKALẸ̀ AJÍLẸ̀ SÍBI ÀKÀNṢE IṢẸ́ AFẸ́FẸ́ GÁÀSÌ ÀTÀWỌN IṢẸ́ ÀKÀNṢE MÌÍRÀN TÍ WỌ́N Ń ṢE NÍ ỌLỌ́KỌLÀ NÍ ÌPÍNLẸ̀ ÒGÙN

ÌKÀNNÌ AMÓHÙN-MÁWÒRÁN YORÙBÁ BROADCASTING NETWORK (YBN) LATI Ń KỌ ÀWỌN ÀKÓJỌPỌ̀ ÌRÒYÌN OLÓJOJÚMỌ́ YÌÍ JÁDE FÚN ÌGBÁDÙN Ẹ̀YIN OLÓLÙFẸ́ WA, Ẹ ṢÉ PÚPỌ̀ FÚN ÌFẸ́ TÍ Ẹ NÍ SÍ WA, ÀJỌṢE WA Ò NÍ BÀJẸ́

Address

Ikoyi

Alerts

Be the first to know and let us send you an email when Yoruba Broadcasting Network YBN posts news and promotions. Your email address will not be used for any other purpose, and you can unsubscribe at any time.

Contact The Business

Send a message to Yoruba Broadcasting Network YBN:

Share