Atọka Iroyin Magazine

Atọka Iroyin Magazine A Yoruba weekly magazine that covers politics,crime, entertainment, sports, culture and general News

Lonii ni ọkan ninu awon aṣofin to n soju ipinle Kogi, Sẹnetọ Natasha Akpoti Uduaghan, ti fẹsun kan adari ileegbimọ aṣofi...
28/02/2025

Lonii ni ọkan ninu awon aṣofin to n soju ipinle Kogi, Sẹnetọ Natasha Akpoti Uduaghan, ti fẹsun kan adari ileegbimọ aṣofin nile Abuja, Sẹnetọ Godswill Akpabio.

Natasha salaye pe, o ti pẹ ti Akpabio ti n wa ọna bo ṣe maa ba oun sun, nitori naa lo ṣe n fooro ẹmi oun. O tu aṣiiri naa lori ifọrọwerọ kan to ṣe lori gbajumọ tẹlifiṣan kan laarọ yii.

18/02/2025

Ninu apoti awọn agba
ỌṢẸ ÌYỌ́NÚ
Esuru pupa, ao gun papo mọ kanhun bilala to mu daadaa,,ao fi ọṣẹ dudu ko o, ao maa fI omi gbigbona wẹ ẹ lalaalẹ
ỌṢẸ RÍRÍṢE
Esuru pupa,ao gun pọ mọ ọpọlọpọ ọṣẹ,ao wa adiẹ pupa, ẹjẹ rẹ ni ao fi po ọṣẹ naa,ao lọ ri adiẹ naa mọ ori akitan,ao maa fi ọṣẹ naa wẹ lalaalẹ pẹlu omi gbigbona, ao fi kun bẹẹ ni ao yọ kuro, fi adura ranṣẹ ko le jẹ fun ẹ.
ASEJẸ AṢÍÍRÍ BÍBÒ TÓ JẸ́
Kidinrin maalu kan,ao ge e si ọna mẹrindinlogun, ao wa ewe tannagbowo ati itanna rẹ,ewe ajeṣẹṣẹfun, iyere mẹrindinlogun,ata ijọsi mẹrindinlogun, ao se e lepo niyọ, ao sọ kalẹ sori oṣuka, ao wa gbadura sii ṣugbọn ko le mu wa kọja aadọta naira o,kii ṣe oogun owo o,aṣiiri bibo lasan ni.lẹyin oṣu kẹta ni o tun le dan an wo.
OÒGÙN ÌSỌ̀YÈ
Ẹye awoko, eye ẹga, ewe oniyeye, odidi atare kan, jijo pọ,a maa da sinu oyin, lila ni o.
AWO IGBA ÀÌSÀN
Tagiiri kan, ao wa ge si wẹwẹ,bara kan ao ge si wẹwẹ,eepo ọsan wẹwẹ ẹru alamọ, kanhun bilala, awusa tutu, ata adayeba, jijo pọ ao da sinu omi ọsan wẹwẹ, mimu laarọ ati lalẹ.
OJÚLÓWÓ ÀGBO ÌWÒSÀN FÚN ÀFẸ́LÙ RỌPÁRỌSẸ̀
Ao wa ọpọlọpọ ewe gbaguda tutu,ewe pia(pear) tutu,ewe esuru pupa tutu, ataalẹ pupa (tumeric), ewe ọsan banbu, eepo ọsan banbu, eepo igi ati ewe koko(cocoa), kanafuru to pọ diẹ,ewe dongoyaro tutu, ao fi omi to mọ daadaa se gbogbo rẹ lagbo ti yo hoo daadaa,ao ma mu ni gbigbona ni gilaasi kọọbu kan laarọ, ati lalẹ fun ọjọ marun leralera,ao ni gburo aisan naa mọ, ẹniti ko ba tii ni rọparọsẹ naa le lo, atẹgun buruku ko nii fẹ lu wa o, awọn to ti ṣe maa gba iwosan laṣẹ Edumare.
OJÚLÓWÓ ÀGUNMU FÚN ÀRÙN ILÉ ÌGBỌ̀NSẸ̀ ỌLỌ́JỌ́ PÍPẸ́ TÓ DÁJÚ
Ko si bo ti le wu ki aisan ileegbọsan buru tabi pẹ lara to, ti o ba fi le fi agunmu yii lo ẹkọ gbigbona, o ni gburo rẹ, mọ alaafia to peye yoo si de ba agọ ara rẹ, ao wa ewe ati egbo iṣirigun gbigbẹ,ewe ati egbo agbosa, ẹfọ yanrin, ao sa ti yoo gbe,taba jukuu,ao sa ti yoo gbẹ,alubọsa aayu,ao sa ti yoo gbẹ,ao gun gbogbo rẹ kunna daadaa,ao tun fi ajọ jọ ọ,ao mo fi ṣibi imukọ ọmọ kekere kan sinu ẹkọ gbigbona laarọ kutukutuki a to jẹun,iwọ naa yoo si ri bi awọn nnkan funfun kan yoo ṣe ma jade nibi itọ rẹ, itọ naa yoo si ma run gidi gan,ma bẹru,awọn nnkan ti ko da lara rẹ ni o n tọ danu yẹn, lo leralera fun ọsẹ kan, ao tọ gbogbo rẹ danu, alaafia to peye yoo si de ba agọ ara wa, dan wo ko fun ile labọ. Yoo jẹ fun yin o.

Sanwó-Olú ṣèfilọ́lẹ̀ ibùdókọ̀ ‘Abúlé Ẹ̀gbá Bus Terminus’Gomina ipinlẹ Eko,  Babajide Sanwo-Olu lanaa ọjọ Iṣẹgun,Tuside k...
18/02/2025

Sanwó-Olú ṣèfilọ́lẹ̀ ibùdókọ̀ ‘Abúlé Ẹ̀gbá Bus Terminus’
Gomina ipinlẹ Eko, Babajide Sanwo-Olu lanaa ọjọ Iṣẹgun,Tuside kede ẹdinwo ida ọgbọn lori owo ọkọ reluwe ‘Red line’ fawọn olugbe Eko.
Sanwo-Olu, firoyin naa sita lasiko to ṣe ifilọlẹ ibudokọ tuntun ni Abule Ẹgba. O ni, igbesẹ naa waye kawọn eeyan le ma wọ ọkọ naa laisi inira lori owo ti wọn maa san.
O ṣalaye pe, ọdun mẹfa sẹyin loun ṣeleri fawọn olugbe Eko pe, wọn maa bẹrẹ si i jẹ igbadun eto irinna igbalode to tun maa ni alopẹ, leyi to maa mu ki lilọ bibọ ọkọ rọrun.
Gẹgẹ bi ọrọ rẹ, lẹyin aṣeyọri lori iṣẹ akanṣe yii, a ti fa a le ẹyin araalu lọwọ, o wa ku si yin lọwọ lati ṣe atunṣe lori ẹ. ‘Owo ẹyin araalu naa la fi ṣe awọn iṣẹ akanṣe yii nitori naa ṣeni ki ẹ ri bi ogun ibi yin kẹẹ si daabobo lọwọ awọn ọmọ ganfe tiwọn ma n ba dukia ijọba jẹ.’
Gomina tẹsiwaju ninu ọrọ rẹ pe, ṣiṣe aṣeyọri lori ibudokọ tiwọn pe ni ‘Abule Ẹgba Bus Terminus’ naa wa ni ibamu pẹlu erongba iṣejọba oun lati sọ Eko di ọtun

Wọ́n fọwọ́ òfín mú àwọn tíwọ́n ń tajà níbi tíjọba kò fọwọ́ sí l’ÉkòóẸṣọ akojanu ipinlẹ Eko, iyẹn Lagos State Taskforce ...
18/02/2025

Wọ́n fọwọ́ òfín mú àwọn tíwọ́n ń tajà níbi tíjọba kò fọwọ́ sí l’Ékòó

Ẹṣọ akojanu ipinlẹ Eko, iyẹn Lagos State Taskforce ti fọwọ ofin mu eeyan mẹrinlelogoji latari bi wọn ṣe n taja nibi tijọba o fọwọsi lori afaara Mile 2 Oke.
Ọga ọlọpaa to lẹwaju ikọ naa, CSP Adetayọ Akerele, ni ṣeni awọn eeyan naa sọ ojuna mọto di ileetaja ti wọn ko si bikita boya wọn ṣediwọ fun eto irinna.
Gẹgẹ bi ọrọ rẹ, oriṣiiriṣii iwe ẹbẹ lawọn awakọ ti kọ ranṣẹ si agọ wọn nibi ti wọn ti pe akiyesi ijọba si bawọn ọlọja naa ṣe maa n jẹ kawọn koju iṣoro sunkẹrẹ fakẹrẹ lojoojumọ koda wọn ni ori afaara ẹlẹsẹ gan ko ṣe e gba fawọn eeyan mọ nitoripe ojuna tooro naa ni wọn fi silẹ tawọn ẹlẹsẹ n gba kọja.
Aye gba awọn ọlọja naa debi pe, wọn ki i jẹ ki mọto rọna gba bọrọ bakan naa ni wọn maa sọrọ ko bakungbe sawọn ẹlẹsẹ bi wọn ba fara gba ọja wọn. O ni, awọn tawọn fọwọ mu naa ti lu ofin eto ayika bakan naa ni wọn tun n ṣe idiwọ fun lilọ bibọ ọkọ leyi to lodi sofin irinna ipinlẹ Eko.
Ọga ọlọpaa naa ni, awọn eeyan naa kan jẹ alaigbọran ni toripe aimọye igba lawọn ti kilọ fun wọn pe ki wọn maṣe taja lori biriiji naa mọ ṣugbọn ti wọn ko gbọ ko to wa di gbe awọn fọwọ ofin mu wọn yii. O ni, gbogbo igba nijọba ma n kede pe kawọn eeyan naa dẹkun ati maa taja lojuna mọto ki wọn si faaye ẹlẹsẹ silẹ fun igbaye rọrun gbogbo eeyan.
Alaga ẹṣọ akojanu naa ti wa ṣekilọ fawọn ọlọja naa pe ki wọn maṣe pada sibẹ mọ nitoripe bi ọwọ ba tun tẹ wọn,ṣeni wọn maa foju wina ofin tiwọn si maa padanu ọja wọn.
Lara nnkan tijọba ṣe koro oju si titaja lojuna marosẹ ni bawọn oniṣẹẹbi kan ṣe n fi awọn ọlọja naa boju lati ja awọn eeyan lole ninu sunkẹrẹ fakẹrẹ.
Awọn ọlọpaa ṣalaye pe, aridaju ti wa pe awọn oniṣẹẹbi naa ma n dibọn bi ẹni to fẹẹ taja ninu sunkẹrẹ fakẹrẹ ọkọ ṣugbọn ṣeni wọn maa yọ ibọn sawọn ero ọkọ tiwọn si ma gba gbogbo ẹru ọwọ wọn ṣugbọn ti ko ba si rira ati tita lojuna,awọn ọkọ a maa lọ geerege bakan naa ni onikaluku maa tete de ilẹ rẹ lasiko.
Gbadeyan Abdulraheem, adari ẹka ikan sara ilu fun ẹka ẹṣọ akojanu naa ni, awọn ti ṣetan lati ṣe afọmọ Eko fun igbaye rọrun tonile talejo.

Ijọba ipinlẹ Ogun ti kede  pe wọn n wa Portable to n pera ẹ ni were olorin, wọn ni kawọn ọlọpaa wa a ni awari
18/02/2025

Ijọba ipinlẹ Ogun ti kede pe wọn n wa Portable to n pera ẹ ni were olorin, wọn ni kawọn ọlọpaa wa a ni awari

Erin wo! Alagba Ayọ Adebanjọ jade laye lẹni ọdun mẹrindinlọgọrun
14/02/2025

Erin wo! Alagba Ayọ Adebanjọ jade laye lẹni ọdun mẹrindinlọgọrun

AWORAN: GOMINA MAKINDE FUN ALAAFIN TUNTUN NI ỌPA AṢẸ
13/01/2025

AWORAN: GOMINA MAKINDE FUN ALAAFIN TUNTUN NI ỌPA AṢẸ

06/01/2025

Latest news coverage, email, free stock quotes, live scores and video are just the beginning. Discover more every day at Yahoo!

Yayi fi aadọta miliọnu naira ta ijọ Ridiimu lọrẹ
05/01/2025

Yayi fi aadọta miliọnu naira ta ijọ Ridiimu lọrẹ

Nítorí owó tí kò tó ra kílìṣi tí wọ́n san, làwọn Ìbàdan ṣe dẹ páńpẹ́ fún mi-PortableGbajumọ olorin igbalode, to tun ma ...
05/01/2025

Nítorí owó tí kò tó ra kílìṣi tí wọ́n san, làwọn Ìbàdan ṣe dẹ páńpẹ́ fún mi-Portable
Gbajumọ olorin igbalode, to tun ma n pera ẹ ni were olorin nni, Habeeb Okikiọla,tawọn eeyan tun mọ si Portable tun ju bọmbu ọrọ kalẹ laipẹ yii. O ni tori owo tiko to nnkan, tiko ju koun fi ra kiliṣi jẹ ti gbajumọ olorin fuji nni,Taye currency san foun, lawọn ọmọ Ibadan ṣe fẹẹ lẹ oun loko pa.
Portable sọ pe, inu yaara igbafẹ loun ṣi wa tawọn kan fi wa ta oun lolobo pe panpẹ rabata niwọn dẹ silẹ foun atipe o ṣeeṣe ki wọn lẹ oun loko pa. O ni, emi kiiṣe Jesu ọmọ Maria o, wọn si fẹ lẹ oko mọ mi nitori ẹ ni mo ṣe yẹra fun wọn kiiṣe pe ẹru ija lo bami o.
Bẹ o ba gbagbe, lasiko ọdun ni Portable lọ silu Ibadan, ko deede lọ o, gbajumọ olorin fuji nni,Taye currency lo pe e ko wa ṣere ọdun fawọn ololufẹ rẹ ṣugbọn tawọn ọmọ Ibadan fi ọmọ ọkọ han an, wọn ni Portable gbọdọ fẹnu gbolẹ lori ọrọ to sọ to fi tabuku ilu wọn lasiko toun ati ololufẹ rẹ tẹlẹ,Dammy ni gbolohun asọ.
Bakan naa ni wọn tun sọ pe yatọ si eyi ti wọn ṣe fun un nilu Ibadan yẹn, o tun maa jẹ iyan rẹ niṣu ni Ọyọ alaafin lọjọkọjọ to ba gbiyanju lati wa sibẹ toripe o tabuku itẹ ọba ti gbogbo ilẹ Yoruba n wari fun.
Ṣao, Portable tun ti sọrọ mi-in sawọn Ibadan o, o ni nitori owo pinniṣin ti ko to oun ra kiliṣi jẹ naa ni wọn ṣe dẹ panpẹ ọran silẹ foun ti wọn fẹ sọ oko le oun lori lai kii ṣe Jesu.

22/11/2024

Emi naa ni idojukọ o,Kunle Afod sọrọ sita

Oṣerekunrin Adeniyi Johnson ni, ẹ gbagbe Bobrisky toripe o ti ba tiẹ lọ. emi Niyirisky de si i yin lọrun bayii
18/11/2024

Oṣerekunrin Adeniyi Johnson ni, ẹ gbagbe Bobrisky toripe o ti ba tiẹ lọ. emi Niyirisky de si i yin lọrun bayii

Address

Lagos

Telephone

+2348134048858

Website

Alerts

Be the first to know and let us send you an email when Atọka Iroyin Magazine posts news and promotions. Your email address will not be used for any other purpose, and you can unsubscribe at any time.

Contact The Business

Send a message to Atọka Iroyin Magazine:

Share