Yoruba Broadcasting Network YBN

Yoruba Broadcasting Network YBN Be free

IROYIN TONI LORI YBN
21/10/2025

IROYIN TONI LORI YBN

LATEST & TRENDING NEWS FOR THE DAY...IROYIN AKOJOPO AGBEYEWO LORI YBN..NIGERIA & YORUBA NATION NEWS LINK: https://youtu.be/VXgs0g5ZDUQFOR M...

20/10/2025

*ÀKÓJỌPỌ̀ ÌRÒYÌN ÒWÚRỌ̀ ÒNÍ OGÚNJỌ́ OṢÙ KẸWÀÁ ỌDÚN 2025*

1. *ÌJỌBA ÀPAPỌ̀ ORÍLẸ̀-ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ TI ṢE ÀFỌ̀MỌ́ Ọ̀RỌ̀ NÍPA ṢÍṢE IṢẸ́ ÌṢIRÒ ÀTI ÈDÈ GẸ̀Ẹ́SÌ TÍ ÀWỌN AKẸ́KỌ̀Ọ́ GIRAMA MA MÁA ṢE KÍ WỌ́N TÓ WỌ ILÉ Ẹ̀KỌ́ GÍGA LÓRÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ*

2. *ÌJỌBA ÀPAPỌ̀ ORÍLẸ̀-ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ TI GBA IṢẸ́ LỌ́WỌ́ ÀWỌN AGBAṢẸ́ṢE TÍ WỌ́N WÁ LÁTI ORÍLẸ̀ ÈDÈ CHINA TÍ WỌ́N Ń ṢE ÀKÀNṢE IṢẸ́ TÓ Ń LỌ LỌ́WỌ́ LÓPÒPÓNÀ PORTHARCOURT SÍ ABÁ LÁTÀRI PÉ IṢẸ́ NÁÀ Ń FALẸ̀*

3. *ILÉ IṢẸ́ ỌLỌ́PÀÁ ORÍLẸ̀-ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ TI FOÙN ÌKÌLỌ̀ SÍTA PÉ ẸNIKẸ́NI Ò GBỌDỌ̀ ṢE ÌWỌ́DE ÌFẸ̀HỌ́NÚHÀN LÁGBÈGBÈ ILÉ ÌJỌBA (A*O ROCK) ÀTI AGBÈGBÈ ÀWỌN ỌMỌ ILÉ ÌGBÌMỌ̀ AṢÒFIN TÓ WÀ NÍ OLÚ ÌLÚ WA ÀBÚJÁ*

4. *GÓMÌNÀ ÌPÍNLẸ̀ Ọ̀ṢUN, ADÉMỌ́LÁ ADÉLÉKÈ TI SẸ́ KANLẸ̀ PÉ IRỌ́ ŃLÁ NI ẸGBẸ́ ÒṢÈLÚ ALL PROGRESSIVES CONGRESS (APC) PA MỌ́ ÒUN, ÒUN Ò FÚN ÀWỌN ADARÍ ẸGBẸ́ ÒṢÌṢẸ́ ÌJỌBA ÌBÍLẸ̀ NÍ ÌPÍNLẸ̀ NÁÀ (NULGE) NÍ OWÓ KỌ́BẸ́ LÁTI MÁ PADÀ SẸ́NU IṢẸ́ WỌN*

5. *ALÁKÒÓSO FÚN ÈTÒ ÌṢÚNÁ LÓRÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ, WÁLÉ ẸDUN TI PADÀ DÉ SÍ ORÍLẸ̀-ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ LÁTI ORÍLẸ̀-ÈDÈ UNITED KINGDOM NÍBI TÍ Ó TI LỌ GBA ÌTỌ́JÚ ÀÌSÀN KAN TÓ Ń BA FÍNRA*

6. *LÁTARI ÈTÒ ÌDÌBÒ ALÁṢẸ TÓ MÁA WÁYÉ NÍ ORÍLẸ̀-ÈDÈ COTE DI VOIRE LÓṢÙ YÌÍ, ÀJỌ ECOWAS TI YAN IGBÁKEJÌ ALÁṢẸ ORÍLẸ̀-ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ TẸ́LẸ̀, YẸMÍ Ọ̀ṢÍNBÀJÒ LÁTI LÉWÁJÚ ÀJỌ NÁÀ LỌ FOJÚ LÁMÉYÌTỌ́ WO ÈTÒ ÌDÌBÒ NÁÀ*

7. *ẸGBẸ́ ÀWỌN OLÙKỌ́ ILÉ Ẹ̀KỌ́ GÍGA ORÍLẸ̀-ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ (ASUU) TI Ń WÒYE ÌGBÉSẸ TÍ ÌJỌBA ÀPAPỌ̀ MÁA GBÉ LÓRÍ BÍ ÌYANṢẸ́LÓDÌ ONÍKÌLỌ̀ WỌN ṢE PÉ Ọ̀SẸ̀ KAN*

8. *AṢÒFIN ÀGBÀ JIBRIN TI SỌ PÉ ÀWỌN ỌMỌ ORÍLẸ̀-ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ MÁA TÓ DẸ́KUN ÀTI LỌ MÁA GBA ÌTỌ́JÚ LÓKÈ ÒKUN*

9. *ÀJỌ TÓ Ń RÍ SÍ Ọ̀RỌ̀ ILÉ IṢẸ́ ỌLỌ́PÀÁ LÓRÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ TI GBA ÀWỌN ỌLỌ́PAA KAN TÍ WỌ́N LÉ KÚRÒ LẸ́NU IṢẸ́ PADÀ SẸ́NU IṢẸ́ LẸ́YÌN ÌWÁDÌÍ ÀWỌN Ẹ̀SÙN TÍ WỌ́N FI KÀN WỌ́N*

10. *ÀWỌN OLÙFẸ̀HỌ̀NÚHÀN TI WỌ́N FẸ́ ṢE ÌWỌ́DE TÓ NÍ ṢE PẸ̀LÚ ÌDÁSÍLẸ̀ NNAMDI KANU NÍLÙÚ ÀBÚJÁ LÓNÌÍ TI SỌ PÉ KÒ SÍ ẸNIKẸ́NI TÓ LÈ DÁ ÀWỌN LỌ́WỌ́ KỌ́*

*OLÚWATÓBILỌ́BA DÁRAMỌ́LÁ (GLAMOURLADY)*

*LÓ Ń JÁBỌ̀ ÌRÒYÌN ÒWÚRỌ̀ ÒNÍ FÚN ÌKÀNNÌ AMÓHÙN-MÁWÒRÁN YORÙBÁ BROADCASTING NETWORK (YBN)*

19/10/2025

*ÀKÓJỌPỌ̀ ÌRÒYÌN ÒWÚRỌ̀ ÒNÍ ỌJỌ́ KỌKÀNDÍNLÓGÚN OṢÙ KẸWÀÁ ỌDÚN 2025*

1. *ALÁṢẸ BỌ́LÁ AHMED TINÚBÚ TI DARÍ PADÀ DÉ SÍ OLÚ ÌLÚ WA ÀBÚJÁ LẸ́YÌN ÌPÀDÉ ÀPÉRÒ ÀWỌN OLÓRÍ ÌJỌBA LÁGBAYÉ TÓ WÁYÉ NÍ ÌLÚ ROME NÍ ORÍLẸ-ÈDÈ ITALY NÍBI TÍ WỌ́N TI JÍRÒRÒ LÓRÍ GÍGBÓGUNTI ÌWÀ ÌGBÉSÙNMỌ̀MÍ LÁWỌN ORÍLẸ̀-ÈDÈ ÀGBÁYÉ*

2. *OLÓRÍ IKỌ̀ ÀWỌN ỌMỌ OGUN TÓ Ń ṢIṢẸ́ LẸ́KÙN ÀRÍWÁ ORÍLẸ̀-ÈDÈ YÌÍ ÌYẸN OPERATION HADIN-KAI, Ọ̀GAGUN ÀBÚBÁKAR TI KÉDE È PÉ ÈTÒ ÀÀBÒ TI BẸ̀RẸ̀ SI NÍ GBÓPỌN LẸ́KÙN ÀRÍWÁ ÌWỌ̀ OÒRÙN ORÍLẸ̀-ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ LẸ́YÌN IṢẸ́ ÈTÒ ÀÀBÒ ALÁGBÁRA TÍ GBOGBO ÀWỌN IKỌ̀ ELÉTÒ ÀÀBÒ GÙN LÉ LÁTI GBÓGUN TI ÀWỌN AGBÉSÙNMỌ̀MÍ*

3. *ÀGBÁRÍJỌPỌ̀ ẸGBẸ́ ÀWỌN OLÓÒTÙ ÌRÒYÌN, ÀWỌN OLÓÒTÚ ÌRÒYÌN LÓRÍ Ẹ̀RỌ AYÉLUJÁRA ÀTI ÀWỌN ILÉ IṢẸ́ ÌGBÓHÙNSÁFẸ́FẸ́ TI SÚN ÌPÀDÉ ÀPÉRÒ WỌN TÓ YẸ KÓ WÁYÉ LỌ́JỌ́ KEJÌLÁ SÍ ỌJỌ́ KẸTÀLÁ OṢÙ KỌKÀNLÁ ỌDÚN YÌÍ*

4. *ẸGBẸ́ ÀWỌN Ọ̀DỌ́ LÓRÍLẸ̀-ÈDÈ YÌÍ (NYC) TI KÌLỌ̀ FÁWỌN Ọ̀DỌ́ LÓRÍLẸ̀ ÈDÈ YÌÍ LÁTI MÁ ṢE KÓPA NÍNÚ ÌFẸ̀HỌ́NÚHÀN TÓ Ń BÉÈRÈ FÚN ÌDÁSÍLẸ̀ ADARÍ IKỌ̀ TÓ Ń JÌJÀGBARA FÚN ORÍLẸ-ÈDÈ BIAFRA (IPOB) ÌYẸN NNAMDI KANU TÓ MÁA WÁYÉ LỌ́LA TÍÍ ṢE OGÚNJỌ́*

5. *ALÁBÒJÚÚTÓ FÚN ÈTÒ ÌLERA NÍ ÌPÍNLẸ̀ ÈKÓ, Ọ̀JỌ̀GBỌ́N AKIN ÀBÁYỌ̀MÍ TI KÉDE RẸ̀ PÉ Ọ̀PỌ̀LỌPỌ̀ Ẹ̀MÍ LÓ Ń SỌNÙ LÁWỌN ÒPÓPÓNÀ MÁROSẸ̀ NÍ ÌPÍNLẸ̀ ÈKÓ LÁTÀRI BÍ ÀWỌN ÈNÌYÀN TÓ YẸ KÓ DÓÒLÀ Ẹ̀MÍ ṢE MÁA Ń KỌ́KỌ́ YA ÀWÒRÁN TÀBÍ FỌ́NRÁN-ÁN ÀWỌN TÓ WÀ NÍNÚ ÌJÀM̀BÁ ỌKỌ̀*

6. *OLÙDÁSÍLẸ̀ ILÉ IṢẸ́ DANGOTE, ALIKO DANGOTE TI RỌ ÀWỌN Ọ̀MỌ́ ORÍLẸ̀-ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ LÁTI MÁA ṢE ÀGBÉLÁRUGẸ ÀWỌN ǸKAN TÍ À Ń PÈSÈ LÓRÍLẸ̀ ÈDÈ YÌÍ KÍ ÈTÒ ỌRỌ̀ AJÉ Ó TÚNBỌ̀ RÚ GỌ́GỌ́ SI*

7. *GÓMÌNÀ TẸ́LẸ̀ NÍ ÌPÍNLẸ̀ KOGÍ, YÀHÀYÁ BÉLLÒ TI RỌ ÀWỌN ỌMỌ ORÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ PÉ KÍ WỌ́N FỌWỌ́SOWỌ́PỌ̀ PẸ̀LÚ ALÁṢẸ BỌ́LÁ TINÚBÚ TORÍ PÉ ÒUN GANGAN NI ÁŃGẸ́LÌ TÍ ỌLỌ́RUN RÁN SÍ ORÍLẸ̀-ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ LÁTI ṢE ÀTÚNṢE RẸ̀*

8. *ÀWỌN ỌMỌ OLÓGUN ORÍLẸ̀-ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ DÓÒLÀ Ẹ̀MÍ ÀWỌN ÈNÌYÀN MÓKÀNLÉLÓGÚN LỌ́WỌ́ ÀWỌN AJÍNIGBÉ NÍ ÌPÍNLẸ̀ KWARA ÀTI ÌPÍNLẸ̀ KOGÍ*

9. *ILÉ IṢẸ́ ỌLỌ́PÀÁ ORÍLẸ̀-ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ TI FOÙN ÌKÌLỌ̀ SÍTA PÉ ÒUN MÁA FI KÉLÉ ÒFIN GBÉ ẸNIKẸ́NI TÍ ỌWỌ́ BÁ TẸ̀ PÉ Ó GBÈRÒ LÁTI ṢE TÀBÍ ṢE ÌWỌ́DE ÌFẸ̀HỌ́NÚHÀN*

10. *ILÉ IṢẸ́ ỌLỌ́PÀÁ RỌ́WỌ́TÓ ÀWỌN AFURASÍ MÁRÙN-ÚN LÓRÍ ÌKỌLÙ TÓ WÁYÉ NÍ AGBÈGBÈ KAN NÍ ÌPÍNLẸ̀ KWARA*

*OLÚWATÓBILỌ́BA DÁRAMỌ́LÁ (GLAMOURLADY)*

*LÓ Ń JÁBỌ̀ ÌRÒYÌN ÒWÚRỌ̀ ÒNÍ FÚN ÌKÀNNÌ AMÓHÙN-MÁWÒRÁN YORÙBÁ BROADCASTING NETWORK (YBN)*

IROYIN TONI LORI YBN
19/10/2025

IROYIN TONI LORI YBN

LATEST & TRENDING NEWS FOR THE DAY...IROYIN AKOJOPO AGBEYEWO LORI YBN..NIGERIA & YORUBA NATION NEWS LINK: https://youtu.be/KHg9g-TgcfMFOR M...

18/10/2025

*ÀKÓJỌPỌ̀ ÌRÒYÌN ÒWÚRỌ̀ ÒNÍ ỌJỌ́ KEJÌDÍNLÓGÚN OṢÙ KẸWÀÁ ỌDÚN 2025*

1. *ÀÀRẸ ẸGBẸ́ ÀWỌN AGBẸJỌ́RÒ LÓRÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ, AFAM OSIGWE TI SỌ PÉ ÀJỌ ELÉTÒ ÌDÌBÒ ORÍLẸ-ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ (INEC) Ò NÍ ÀṢẸ LÁBẸ́ ÒFIN LÁTI SỌ PÉ ÀÀYÈ GÓMÌNÀ KAN SÓFO LÁTÀRI PÉ Ó KÚRÒ NÍNÚ ẸGBẸ́ ÒṢÈLÚ KAN LỌ SÍ ÒMÍRÀN*

2. *ILÉ ẸJỌ́ GÍGA LÓLÚ ÌLÚ WA ÀBÚJÁ TI DÁ ỌMỌ́YẸLÉ ṢÒWÒRẸ́ ÀTI ÀWỌN TÓ KÙ LỌ́WỌ́ KỌ́ LÁTI MÁ ṢÈTÒ ÌFẸ̀HỌ́NÚHÀN LÓRÍ ÌDÁSÍLẸ̀ ADARÍ IKỌ̀ TÓ Ń PÈ FÚN ORÍLẸ̀-ÈDÈ BIAFRA, NNAMDI KANU TÍ WỌ́N Ń ṢÈTÒ Ẹ̀ LÁTI WÁYÉ LỌ́JỌ́ AJÉ TÍÍ ṢE OGÚNJỌ́ OṢÙ KẸWÀÁ*

3. *ÌJỌBA ÌPÍNLẸ̀ ÈKÌTÌ TI ṢE ÌFÍLỌ́LẸ̀ IBÙDÓ TÍ WỌ́N Ń KÓ ÒÒGÙN SÍ LÁTI LÈ DÈNÀ ÀWỌN OÒGÙN AYÉDÈRÚ TÍ ỌJỌ́ TI LỌ LÓRÍ WỌN*

4. *ILÉ IṢẸ́ ORÍLẸ̀-ÈDÈ AMẸ́RÍKÀ LÓRÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ TI KÌLỌ̀ ÈTÒ ÀÀBÒ FÚN ÀWỌN ỌMỌ ORÍLẸ̀-ÈDÈ WỌN ṢÁÁJÚ ÌFẸ̀HỌ́NÚHÀN ÀWỌN TÓ Ń BÉÈRÈ FÚN ÌDÁSÍLẸ̀ ADARÍ IKỌ̀ TÓ Ń PÈ FÚN ORÍLẸ̀-ÈDÈ BIAFRA, NNAMDI KANU TÓ MÁA WÁYÉ LỌ́JỌ́ AJÉ TÍÍ ṢE OGÚNJỌ́ OṢÙ KẸWÀÁ*

5. *ILÉ IṢẸ́ ẸBU ÌFỌPO DANGOTE TI JẸ́ KÓ DI MÍMỌ̀ PÉ ÒUN TI ṢE ÀKỌ́SÍLẸ̀ ÀWỌN ÌWÀ MỌ̀DÀRÚ TÓ TÓ MÉJÌLÉLÓGÚN LÁTI ÌGBÀ TÍ WỌ́N TI DÁA SÍLẸ̀*

6. *ÀWỌN ỌMỌ ẸGBẸ́ ÒṢÈLÚ ALL PROGRESSIVES CONGRESS NÍ ÌPÍNLẸ̀ PLATEAU TI BỌWỌ̀ LU ALÁṢẸ BỌ́LÁ TINÚBÚ GẸ́GẸ́ BÍ ALÁṢẸ NÍNÚ ÌDÌBÒ ỌDÚN 2027 LÉYÌÍ TÍ WỌ́N WÁ KORÒ OJÚ SÍ BÍ GÓMÌNÀ ÌPÍNLẸ̀ PLATEAU,CALEB MUFTWANG ṢE FẸ́ DIGBÁDAGBỌ̀N Ẹ̀ TA KỌ́ṢỌ́ SÍNÚ ẸGBẸ́ ÒṢÈLÚ NÁÀ*

7. *AJÌJÀGBARA ÀWÙJỌ OBÌNRIN NÌ, TÍ Ó TÚN JẸ́ AJÀFẸ́TỌ̀ ỌMỌNÌYÀN, AISHA YÉSÚFÙ TI SỌ̀RỌ̀ JÁDE PÉ ÀÀYÈ ÀTI ÀǸFÀÀNÍ ŃLÁ WÀ FÚN ADÍJEDUPÒ ALÁṢẸ LÁBẸ́ ÀSÍÁ ẸGBẸ́ ÒṢÈLÚ LABOUR PARTY, PETER OBI NÍNÚ ÌDÌBÒ ÀPAPỌ̀ TÓ MÁA WÁYÉ LỌ́DÚN 2027 JÚ ÌDÌBÒ ÀPAPỌ̀ TÓ TI WÁYÉ LỌ́DÚN 2023 LỌ*

8. *ÀWỌN AṢOJÚ ORÍLẸ̀-ÈDÈ AMẸ́RÍKÀ TI JẸ́ KÓ DI MÍMỌ̀ PÉ ÀWỌN AGBÉSÙNMỌ̀MÍ Ń ṢEKÚ PA ÀWỌN ẸLẸ́SÌN MÙSÙLÙMÍ PÚPỌ̀ NÍ ORÍLẸ̀-ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ*

9. *ỌWỌ́ ILÉ IṢẸ́ ỌLỌ́PAA ÌPÍNLẸ̀ BAUCHI TI TẸ OKÙNRIN KÀN ỌMỌ ỌGBỌ̀N ỌDÚN TÍ ORÚKỌ̀ RẸ̀ Ń JẸ́ MAMUDA ZAKARI YAU LÓRÍ Ẹ̀SÙN PÉ Ó GÚN ỌLỌ́KADÀ KAN PA, Ó SÌ JÍ ỌKADÀ NÁÀ LÁTI LÈ RÍ OWÓ ṢE ÌGBÉYÀWÓ*

10. *ÀWỌN AGBÉBỌN ṢEKÚ PA ÀWỌN ỌLỌ́PÀÁ MÉJÌ NÍNÚ ÌKỌLÙ TÓ WÁYÉ NÍ ÌPÍNLẸ̀ KÀDÚNÁ*

*OLÚWATÓBILỌ́BA DÁRAMỌ́LÁ (GLAMOURLADY)*

*LÓ Ń JÁBỌ̀ ÌRÒYÌN ÒWÚRỌ̀ ÒNÍ FÚN ÌKÀNNÌ AMÓHÙN-MÁWÒRÁN YORÙBÁ BROADCASTING NETWORK (YBN)*

IROYIN TONI LORI YBN
18/10/2025

IROYIN TONI LORI YBN

LATEST & TRENDING NEWS FOR THE DAY...IROYIN AKOJOPO AGBEYEWO LORI YBN..NIGERIA & YORUBA NATION NEWS LINK: https://youtu.be/fjRtJEfCuCwFOR M...

17/10/2025

*ÀKÓJỌPỌ̀ ÌRÒYÌN ÒWÚRỌ̀ ÒNÍ ỌJỌ́ KẸTÀDÍNLÓGÚN OṢÙ KẸWÀÁ ỌDÚN 2025*

1. *ALÁKÒÓSO FÚN Ọ̀RỌ̀ IṢẸ́ NÍ ILẸ̀ WA DAVID UMAHI TI GBA ẸNU ÌJỌBA ÀPAPỌ̀ ORÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ BẸNU ÀTẸ́ LU ÀWỌN ÌRÒYÌN KAN TÓ Ń TÀN KÁLẸ̀ PÉ IṢẸ́ ÀKÀNṢE ÒPÓPÓNÀ MÁROSẸ̀ TÓ Ń LỌ LỌ́WỌ́ NÍ Ọ̀RẸ̀ TÍTÍ DÉ ÌLÚ ÀKÚRẸ́ NÍ ÌPÍNLẸ̀ ÒǸDÓ KÒ PÓJÚ ÒṢÙWỌ̀N RÁRÁ*

2. *ÀWỌN ỌMỌ ILÉ ÌGBÌMỌ̀ AṢÒFIN ÀGBÀ ILẸ̀ WA TI FÌDÍ Ọ̀JỌ̀GBỌ́N JOASH ÀMÚPÌTÀN MÚLẸ̀ GẸ́GẸ́ BÍ ALÁGA ÀJỌ TÓ Ń RÍ SÍ ÈTÒ ÌDÌBÒ ÀPAPỌ̀ LÓRÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ (INEC)*

3. *GÓMÌNÀ ÌPÍNLẸ̀ ÈKÌTÌ, BÍỌ́DÚN OYÈBÁNJÍ TI PÈ FÚN ÌṢỌ̀KAN LÁÀRÍN ÀWỌN ALÁTÌLẸYÌN RẸ̀ ÀTI ÀWỌN ỌMỌ ẸGBẸ́ ÒṢÈLÚ ALL PROGRESSIVES CONGRESS ṢÁÁJÚ ÈTÒ ÌDÌBÒ GÓMÌNÀ TÓ MÁA WÁYÉ NÍ OGÚNJỌ́ OṢÙ NÍ ÌPÍNLẸ̀ ÈKÌTÌ*

4. *ÌJỌBA ÀPAPỌ̀ ORÍLẸ̀-ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ TI NÍ ÀFOJÚSÙN LÁTI MÁA PÈSÈ ÀGBÁ EPO RỌ̀BÌ TÓ TÓ ẸGBẸ̀RÚN LỌ́NA ẸGBẸ̀TA LÓJOOJÚMỌ́ LÁTI LÈ FA OJÚ Ọ̀PỌ̀LỌPỌ̀ ÀWỌN OLÙDÓKOÒWÒ MỌ́RA LẸ́KA NÁÀ*

5. *ẸGBẸ́ ÀWỌN ONÍMỌ̀ ÌṢÈGÙN LÓRÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ TI FÌDÍ Ẹ̀ MÚLẸ̀ PÉ ÀÌSÀN TÓ Ń ṢE OLÓRÍ IKỌ̀ TÓ Ń PÈ FÚN ÌDÁSÍLẸ̀ ORÍLẸ̀-ÈDÈ BIAFRA (IPOB) ÌYẸN NNAMDI KANU KÌÍ ṢE ÈYÍ TÓ Ń DÚNKOKÒ MỌ́ Ẹ̀MÍ ÈNÌYÀN LẸ́YÌN TÍ WỌ́N ṢE ÌWÁDÌÍ ÀÌSÀN NÁÀ KÓ TÓ DI PÉ ILÉ ẸJỌ́ TẸ̀SÍWÁJÚ LÓRÍ ÌGBẸ́JỌ́ RẸ̀*

6. *ẸGBẸ́ OHANEZE NDIGBO PẸ̀LÚ ÌFỌWỌ́SOWỌ́PỌ̀ ÀWỌN GÓMÌNÀ APÁ ÌWỌ̀ OÒRÙN GÚÚSÙ ÀTI APÁ ÌLÀ OÒRÙN GÚÚSÙ ORÍLẸ̀-ÈDÈ YÌÍ ÀTÀWỌN ỌMỌ ILÉ ÌGBÌMỌ̀ AṢÒFIN TÍ WỌ́N JẸ́ Ẹ̀YÀ IGBO TI JẸ́ KÓ DI MÍMỌ̀ PÉ ÀWỌN Ò LỌ́WỌ́ NÍNÚ ÌFẸ̀HỌ́NÚHÀN ÀPAPỌ̀ TÍ ÀWỌN KÀN Ń GBÈRÒ Ẹ̀ NÍ OGÚNJỌ́ OṢÙ KẸWÀÁ ỌDÚN YÌÍ*

7. *ÌGBÌMỌ̀ ADARÍ LÓLÚ ÌLÚ WA ÀBÚJÁ TI DA ÀWỌN ILÉ MỌ́KÀNLÁ Ọ̀TỌ̀Ọ̀TỌ̀ KAN WÓ NÍ ÌLÚ ÀBÚJÁ LÁTÀRI PÉ WỌ́N LÒDÌ SÍ ÒFIN KÍKỌ́LÉ NÍ ÌLÚ ÀBÚJÁ BẸ́Ẹ̀ NI WỌ́N WÁ KÌLỌ̀ FÚN ÀWỌN ILÉ IṢẸ́ ABÁNIKỌ́LÉ NÍ ÌLÚ ÀBÚJÁ PÉ WỌ́N MA FOJÚ WINNÁ ÒFIN BÍ WỌ́N BÁ KỌ̀ LÁTI GBỌ́NRÀN*

8. *AKỌ̀WÉ FÚN ÌJỌBA ÀPAPỌ̀ ORÍLẸ̀-ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ, GEORGE AKUME TI SỌ FÚN ÀWỌN ẸGBẸ́ TÓ NÍ ṢE PẸ̀LÚ ÈTÒ ỌRỌ̀ AJÉ ÌYẸN NACCIMA PÉ KÍ WỌ́N ṢE ÀTÌLẸYÌN SÍ ÌGBÉSẸ̀ TÍ ALÁṢẸ BỌ́LÁ TINÚBÚ Ń GBÉ LÓRÍ Ọ̀RỌ̀ ÈTÒ ỌRỌ̀ AJÉ*

9. *IJỌBA ÀPAPỌ̀ ORÍLẸ̀-ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ TI ṢETÁN LÁTI FI IṢẸ́ TÓ NÍ ṢE PẸ̀LÚ NÍPA MÍ MÁA KỌ́ NÍPA Ẹ̀KỌ́ ÀÀMÌ ÌYẸN SIGN LANGUAGE SÍNÚ IṢẸ́ TÍ ÀWỌN AKẸ́KỌ̀Ọ́ YÓÒ MÁA KỌ́ LÁWỌN ILÉ Ẹ̀KỌ́ GBOGBO*

10. *ILÉ IṢẸ́ ỌLỌ́PÀÁ ORÍLẸ̀-ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ TI RÍ ÀṢẸ ILÉ ẸJỌ́ GBÀ LÁTI FI OJÚ ÀWỌN ARÁ ILẸ̀ ÒKÈÈRÈ MỌ́KÀNDÍNLỌ́GỌ́TA HÀN LÓRÍ Ẹ̀SÙN PÉ WỌ́N Ń LU JÌBÌTÌ ORÍ Ẹ̀RỌ AYÉLUJÁRA*

*OLÚWATÓBILỌ́BA DÁRAMỌ́LÁ (GLAMOURLADY)*

*LÓ Ń JÁBỌ̀ ÌRÒYÌN ÒWÚRỌ̀ ÒNÍ FÚN ÌKÀNNÌ AMÓHÙN-MÁWÒRÁN YORÙBÁ BROADCASTING NETWORK (YBN)*

IROYIN TONI LORI YBN
17/10/2025

IROYIN TONI LORI YBN

LATEST & TRENDING NEWS FOR THE DAY...IROYIN AKOJOPO AGBEYEWO LORI YBN..NIGERIA & YORUBA NATION NEWS LINK: https://youtu.be/72UbkR97oP4FOR M...

16/10/2025

*ÀKÓJỌPỌ̀ ÌRÒYÌN ÒWÚRỌ̀ ÒNÍ ỌJỌ́ KẸRÌNDÍNLÓGÚN OṢÙ KẸWÀÁ ỌDÚN 2025*

1. *Ẹ̀KA ILÉ IṢẸ́ ÌJỌBA ÀPAPỌ̀ TÓ Ń RÍ SÍ ÈTÒ Ẹ̀KỌ́ṢẸ́ ỌWỌ́ TI ṢE ÀYẸ̀WÒ ÀWỌN ONÍṢẸ́ ỌWỌ́ TÓ TÓ ẸGBẸ̀RÚN MẸ́Ẹ̀DÓGÚN NÍ ÌPÍNLẸ̀ PLATEAU LÁTI LÈ RÓ WỌN LÁGBÁRA*

2. *WỌ́N TI ṢE ÀTÚNYÀN ALÁGA ÀJỌ TÓ Ń RÍ SÍ Ọ̀RỌ̀ ÌWÀ ÌBÀJẸ́ ÀTI ṢÍṢE OWÓ ÌLÚ MỌKUMỌ̀KU LÓRÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ (EFCC) ÌYẸN ỌLÁ OLÚKÓYÈDÉ GẸ́GẸ́ BÍ ÀÀRẸ IKỌ̀ TÓ Ń GBÓGUN TI ÌWÀ ÌBÀJẸ́ NÍ ÌWỌ̀ OÒRÙN ÁFRÍKÀ (NACCIMA)*

3. *GÓMÌNÀ ÌPÍNLẸ̀ BAYELSA DUOYE DIRI NÁÀ TI DIGBÁDAGBỌ̀N Ẹ̀ KÚRÒ NÍNÚ ẸGBẸ́ ÒṢÈLÚ PEOPLES DEMOCRATIC PARTY(PDP) LỌ SÍNÚ ẸGBẸ́ ÒṢÈLÚ ALL PROGRESSIVES CONGRESS(APC) NÍTORÍ ÀWỌN GBÓDÓNRÓṢỌ TÓ Ń FI IGBAGBOGBO ṢẸLẸ̀ NÍNÚ ẸGBẸ́ ÒṢÈLÚ NÁÀ*

4. *ÀJỌ KAN TÍ WỌ́N PERA WỌN NÍ PESMDAA TÍ WỌ́N Ń GBÓGUN TI ÌWÀ ÌBÀJẸ́ LẸ́KA EPO PẸTIRÓÒLÙ ÀTI ÌWAKÙSÀ LỌ́NÀ TÍ KÒ BÓFIN MU MÁA ṢE ÌFILỌ́LẸ̀ ÀWỌN ÌGBÌMỌ̀ ADARÍ NÍ ÌPÍNLẸ̀ ÒGÙN ÀTI ÀWỌN ÌJỌBA ÌBÍLẸ̀ OGÚN TÓ WÀ NÍ ÌPÍNLẸ̀ ÒGÙN*

5. *GÓMÌNÀ TẸ́LẸ̀ NÍ ÌPÍNLẸ̀ ÈKÌTÌ, AYỌ̀DÉLÉ FÁYỌ̀ṢE TI SỌ̀RỌ̀ SÍTA PÉ ÒUN Ò NÍ ÈRÒNGBÀ LÁTI TÚN WÀ NÍPÒ ÌJỌBA MỌ LÒUN Ò ṢE GBA IPÒ KANKAN LỌ́WỌ́ ALÁṢẸ BỌ́LÁ TINÚBÚ*

6. *AṢÒFIN SERIAK DICKSON LÁTI ÌPÍNLẸ̀ BAYELSA FẸ̀SÙN KAN ÀWỌN GÓMÌNÀ ÀTI ÀWỌN ÀGBÀ ÒṢÈLÚ TÍ WỌ́N Ń KÚRÒ NÍNÚ ẸGBẸ́ ÒṢÈLÚ PEOPLES DEMOCRATIC PARTY (PDP) LỌ SÍNÚ ẸGBẸ́ ÒṢÈLÚ ALL PROGRESSIVES CONGRESS (APC) PÉ ÌWÀ ÌBÀJẸ́ ÀTI ÌWÀ ÌDỌ̀TÍ TÍ WỌ́N TI HÙ NÍNÚ ẸGBẸ́ ÒṢÈLÚ NÁÀ LÓ FÀÁ TÍ WỌ́N FI Ń SÁ KIRI*

7. *YÙNGBA YÙNGBA NI INÚ ÀWỌN OLÙGBÉ ÌLÚ ÌBÀDÀN Ń DÙN LÁTÀRI BÍ IKỌ̀ Ẹ̀ṢỌ́ AṢỌ́BODÈ ṢE Ń TA ÀWỌN EPO PẸTIRÓÒLÙ TÍ WỌ́N GBÀ LỌ́WỌ́ ÀWỌN ONÍFÀYÀWỌ́ NÍ ẸGBẸ̀TA NÁÍRÀ FÚN WỌN*

8. *ILÉ ẸJỌ́ GÍGA KÀN NÍ ÌPÍNLẸ̀ KÁNÒ TI PÀṢẸ PÉ KÍ AKỌ́NIMỌ̀Ọ́GBÁ KAN TÍ ORÚKỌ KÀN Ń JẸ́ HAYATU MOHAMMED MÁA LỌ SÍNÚ ỌGBÀ ÀTÚNṢE FÚN ỌDÚN MẸ́JỌ LÁTÀRI PÉ Ó ṢE YÙNKẸ́YÙNKẸ́ AKỌSÁKỌ PẸ̀LÚ Ọ̀KAN NÍNÚ ÀWỌN TÓ Ń KỌ́ LẸ́Ẹ̀MEJÌ Ọ̀TỌ̀Ọ̀TỌ̀*

9. *IJỌBA ÀPAPỌ̀ ṢE ÀFỌ̀MỌ́ Ọ̀RỌ̀ LÓRÍ GBÍGBA ÀWỌN ỌMỌ ILẸ̀ ÒKÈÈRÈ SẸ́NU IṢẸ́ LÓRÍLẸ̀ ÈDÈ YÌÍ*

10. *ILÉ ÌGBÌMỌ̀ AṢÒFIN ÀGBÀ ORÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ BẸ̀RẸ̀ ÌWÁDÌÍ LÓRÍ ÈTÒ ÀÀBÒ ÌGBÒKÈGBODÒ ỌKỌ̀ ÒFURUFÚ NÍ ILẸ̀ WA*

*OLÚWATÓBILỌ́BA DÁRAMỌ́LÁ (GLAMOURLADY)*

*LÓ Ń JÁBỌ̀ ÌRÒYÌN ÒWÚRỌ̀ ÒNÍ FÚN ÌKÀNNÌ AMÓHÙN-MÁWÒRÁN YORÙBÁ BROADCASTING NETWORK (YBN)*

IROYIN TONI LORI YBN
16/10/2025

IROYIN TONI LORI YBN

LATEST & TRENDING NEWS FOR THE DAY...IROYIN AKOJOPO AGBEYEWO LORI YBN..NIGERIA & YORUBA NATION NEWS LINK: https://youtu.be/SWNzRfkkK2EFOR M...

15/10/2025

*ÀKÓJỌPỌ̀ ÌRÒYÌN ÒWÚRỌ̀ ÒNÍ ỌJỌ́ KẸẸ̀DÓGÚN OṢÙ KẸWÀÁ ỌDÚN 2025*

1. *ALÁṢẸ BỌ́LÁ TINÚBÚ TI PE ÌPÈ LÁTI SỌ MÍ MÁA WAKÙSÀ LỌ́NÀ ÀÌTỌ́ ÀTI MÍ MÁA JÍ ÀWỌN OUN ÀLÙMỌ́Ọ́NÌ INÚ ILẸ̀ DI ÌWÀ Ọ̀DARÀN LẸ́KÙN ÌWỌ̀ OÒRÙN ÁFRÍKÀ*

2. *ÌJỌBA ÀPAPỌ̀ ORÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ TI JẸ́ KÓ DI MÍMỌ̀ PÉ IṢẸ́ ÌMỌ̀ ÈTÒ ÈKỌ́ ÌṢIRÒ (MATHEMATICS) Ò PỌNDANDAN MỌ́ FÚN ÀWỌN TÓ BÁ FẸ́ WỌLÉ KẸ́KỌ̀Ọ́ NÍPA Ọ̀RỌ̀ ÀṢÀ ÀTI Ọ̀RỌ̀ ỌMỌNIYAN LÁWỌN ILÉ Ẹ̀KỌ́ GÍGA TÓ WÀ LÓRÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ*

3. *GÓMÌNÀ ÌPÍNLẸ̀ ENUGU PETER MBAH TI DIGBÁDAGBỌ̀N Ẹ̀ KÚRÒ NÍNÚ ẸGBẸ́ ÒSÈLÚ PEOPLES DEMOCRATIC PARTY(PDP) LỌ SÍNÚ ẸGBẸ́ ÒṢÈLÚ ALL PROGRESSIVES CONGRESS(APC) NÍTORÍ ÀWỌN GBÓDÓNRÓṢỌ TÓ Ń FI IGBAGBOGBO ṢẸLẸ̀ NÍNÚ ẸGBẸ́ ÒṢÈLÚ NÁÀ*

4. *ẸGBẸ́ KAN TÓ FÍ ARA JỌ ẸGBẸ́ ÒṢÈLÚ NÍ ÌPÍNLẸ̀ ENUGU TI GBÓṢÙBÀ RÀBÀǸDẸ̀ FÚN GÓMÌNÀ ÌPÍNLẸ̀ NÁÀ, PETER MBAH PÉ ÌGBÉSẸ̀ TÓ DÁRA GIDI GAN LÓ GBÉ LÓRÍ BÓ ṢE DIGBÁDAGBỌ̀N Ẹ̀ KÚRÒ NÍNÚ ẸGBẸ́ ÒṢÈLÚ PEOPLES DEMOCRATIC PARTY (PDP) LỌ SÍNÚ ẸGBẸ́ ÒṢÈLÚ ALL PROGRESSIVES CONGRESS(APC)*

5. *ÀWỌN ỌMỌ ILÉ ÌGBÌMỌ̀ AṢÒFIN ÌPÍNLẸ̀ ÒGÙN TI Ń GBÉ ÌGBÉSẸ̀ LÁTI FI ÒFIN DE ÀWỌN ṢARINṢARIN NÍ ÀWỌN ÀDÚGBÒ GBOGBO NÍ ÌPÍNLẸ̀ ÒGÙN LÁTÀRI ÀWỌN ÌWÀ ÀÌTỌ́ TÍ WỌ́N Ń HÙ*

6. *ẸGBẸ́ ÒṢÈLÚ AFRICAN DEMOCRATIC CONGRESS (ADC) TI SỌ PÉ ÀWỌN Ò FẸ́ , BẸ́Ẹ̀ SÌ NI AWỌN ỌMỌ ILÉ ÌGBÌMỌ̀ AṢÒFIN ÀGBÀ Ò GBỌDỌ̀ BỌWỌ́ LU ÀBÁ TÓ DÁ LÓRÍ ÀTI DÌBÒ ÀPAPỌ̀ ALÁṢẸ ÀTI ÌBÒ GÓMÌNÀ TÓ YẸ KÓ WÁYÉ LỌ́DÚN 2027 NÍ OṢÙ KỌKÀNLÁ ỌDÚN 2026*

7. *ÌJỌBA ÀPAPỌ̀ ÀTI ÀJỌ TÓ Ń RÍ SÍ Ọ̀NÀ INÁ MỌ̀NÀMỌ́NÁ LÓRÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ TI BỌWỌ́LU OWÓ TÙÙLÙTUULU TÓ LÉ NÍ TÍRÍLÍỌ́NÙ LÁTI LÈ FI SAN ÀWỌN GBÈSÈ TÍ ORÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ JẸ LẸ́KA INÁ ỌBA*

8. *Ọ̀KAN LÁRA AGBẸJỌ́RÒ NÍ ÌPÍNLẸ̀ ÒGÙN TI KỌ̀WÉ RÁNṢẸ́ SÍ GÓMÌNÀ ÌPÍNLẸ̀ ÒGÙN, ỌMỌBA DÀPỌ̀ ABÍỌ́DÚN LÁTI WÁ ṢÀLÀYÉ LÁÀRÍN ỌJỌ́ MÉJE ÀWỌN IYE OWÓ TÍ Ó NÁ LÓRÍ ÀWỌN Ọ̀NÀ LÁTI ỌDÚN 2019 SÍ ỌDÚN 2025 TÍ A WÀ YÌÍ*

9. *ÀWỌN ỌMỌ ILÉ ÌGBÌMỌ̀ AṢÒFIN ÀGBÀ LÓRÍLẸ̀ ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ TI DÁ SÍ LỌGBỌLỌGBỌ TÓ Ń ṢẸLẸ̀ LÁÀRÍN ẸGBẸ́ ASUU ÀTI ÌJỌBA ÀPAPỌ̀ KÍ ÌYANṢẸ́LÓDÌ WỌN Ó LE DÚRÓ WÁPE*

10. *IKỌ̀ ÀWỌN ỌMỌ OLÓGUN ORÍLẸ̀-ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ TI NAWỌ́ GÁN ÀWỌN KÀN TÍ WỌ́N JẸ́ AGBÓDEGBÀ TÍ WỌ́N SÌ Ń KÓ ÀWỌN OUN ÌJÀ OLÓRÓ FÚN ÀWỌN AGBÉSÙNMỌ̀MÍ*

*OLÚWATÓBILỌ́BA DÁRAMỌ́LÁ (GLAMOURLADY)*

*LÓ Ń JÁBỌ̀ ÌRÒYÌN ÒWÚRỌ̀ ÒNÍ FÚN ÌKÀNNÌ AMÓHÙN-MÁWÒRÁN YORÙBÁ BROADCASTING NETWORK (YBN)*

IROYIN TONI LORI YBN
15/10/2025

IROYIN TONI LORI YBN

LATEST & TRENDING NEWS FOR THE DAY...IROYIN AKOJOPO AGBEYEWO LORI YBN..NIGERIA & YORUBA NATION NEWS LINK: https://youtu.be/mm6_kb6P_XoFOR M...

Address

7 Akinolu Str, Victoria Island
Lagos
100001

Alerts

Be the first to know and let us send you an email when Yoruba Broadcasting Network YBN posts news and promotions. Your email address will not be used for any other purpose, and you can unsubscribe at any time.

Contact The Business

Send a message to Yoruba Broadcasting Network YBN:

Share